Àìsáyà 60:1-22

  • Ògo Jèhófà tàn sórí Síónì (1-22)

    • Bí àwọn àdàbà tó ń fò lọ sí ilé wọn (8)

    • Wúrà dípò bàbà (17)

    • Ẹni tó kéré máa di ẹgbẹ̀rún (22)

60  “Dìde, ìwọ obìnrin,+ tan ìmọ́lẹ̀, torí ìmọ́lẹ̀ rẹ ti dé. Ògo Jèhófà ń tàn sára rẹ.+   Torí, wò ó! òkùnkùn máa bo ayé,Ìṣúdùdù tó kàmàmà sì máa bo àwọn orílẹ̀-èdè;Àmọ́ Jèhófà máa tàn sára rẹ,Wọ́n sì máa rí ògo rẹ̀ lára rẹ.   Àwọn orílẹ̀-èdè máa lọ sínú ìmọ́lẹ̀ rẹ,+Àwọn ọba+ sì máa lọ sínú ẹwà rẹ tó ń tàn.*+   Gbé ojú rẹ sókè, kí o sì wò yí ká! Gbogbo wọn ti kóra jọ; wọ́n ń bọ̀ lọ́dọ̀ rẹ. Àwọn ọmọkùnrin rẹ ń bọ̀ láti ọ̀nà jíjìn,+Ẹ̀gbẹ́ ni wọ́n sì gbé àwọn ọmọbìnrin rẹ sí.+   Ní àkókò yẹn, o máa rí i, o sì máa tàn yinrin,+Ọkàn rẹ máa lù kìkì, ó sì máa kún rẹ́rẹ́,Torí pé a máa darí ọrọ̀ òkun sọ́dọ̀ rẹ;Àwọn ohun àmúṣọrọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè máa wá sọ́dọ̀ rẹ.+   Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ràkúnmí máa bo ilẹ̀ rẹ,*Àwọn akọ ọmọ ràkúnmí Mídíánì àti Eéfà.+ Gbogbo àwọn tó wá láti Ṣébà, wọ́n máa wá;Wọ́n máa gbé wúrà àti oje igi tùràrí. Wọ́n máa kéde ìyìn Jèhófà.+   A máa kó gbogbo agbo ẹran Kídárì+ jọ sọ́dọ̀ rẹ. Àwọn àgbò Nébáótì+ máa sìn ọ́. Wọ́n máa wá sórí pẹpẹ mi pẹ̀lú ìtẹ́wọ́gbà,+Màá sì ṣe ilé ológo mi* lọ́ṣọ̀ọ́.+   Àwọn wo nìyí tí wọ́n ń fò kọjá bí ìkùukùu,Bí àwọn àdàbà tó ń fò lọ sí ilé* wọn?   Torí àwọn erékùṣù máa gbẹ́kẹ̀ lé mi,+Àwọn ọkọ̀ òkun Táṣíṣì ló ṣíwájú,*Láti kó àwọn ọmọ rẹ wá láti ọ̀nà jíjìn,+Pẹ̀lú fàdákà wọn àti wúrà wọn,Síbi orúkọ Jèhófà Ọlọ́run rẹ àti sọ́dọ̀ Ẹni Mímọ́ Ísírẹ́lì,Torí ó máa ṣe ọ́ lógo.*+ 10  Àwọn àjèjì máa mọ àwọn ògiri rẹ,Àwọn ọba wọn sì máa ṣe ìránṣẹ́ fún ọ,+Torí ìbínú ni mo fi kọ lù ọ́,Àmọ́ màá fi ojúure* mi ṣàánú rẹ.+ 11  Àwọn ẹnubodè rẹ máa wà ní ṣíṣí nígbà gbogbo;+Wọn ò ní tì wọ́n ní ọ̀sán tàbí ní òru,Láti mú ohun àmúṣọrọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè wá sọ́dọ̀ rẹ,Àwọn ọba wọn sì máa ṣáájú.+ 12  Torí orílẹ̀-èdè àti ìjọba èyíkéyìí tí kò bá sìn ọ́ máa ṣègbé,Àwọn orílẹ̀-èdè sì máa pa run pátápátá.+ 13  Ọ̀dọ̀ rẹ ni ògo Lẹ́bánónì máa wá,+Igi júnípà, igi áàṣì àti igi sípírẹ́sì lẹ́ẹ̀kan náà,+Láti ṣe ibi mímọ́ mi lọ́ṣọ̀ọ́;Màá ṣe ibi tí ẹsẹ̀ mi wà lógo.+ 14  Àwọn ọmọ àwọn tó fìyà jẹ ọ́ máa wá, wọ́n á sì tẹrí ba níwájú rẹ;Gbogbo àwọn tó ń hùwà àfojúdi sí ọ gbọ́dọ̀ tẹrí ba níbi ẹsẹ̀ rẹ,Wọ́n sì máa pè ọ́ ní ìlú Jèhófà,Síónì Ẹni Mímọ́ Ísírẹ́lì.+ 15  Dípò kí wọ́n pa ọ́ tì, kí wọ́n sì kórìíra rẹ, láìsí ẹni tó ń gbà ọ́ kọjá,+Màá mú kí o di ohun àmúyangàn títí láé,Orísun ayọ̀ láti ìran dé ìran.+ 16  O sì máa mu wàrà àwọn orílẹ̀-èdè,+O máa mu ọmú àwọn ọba;+Wàá sì mọ̀ dájú pé èmi Jèhófà ni Olùgbàlà rẹ,Alágbára Jékọ́bù sì ni Olùtúnrà rẹ.+ 17  Dípò bàbà, màá mú wúrà wá,Dípò irin, màá mú fàdákà wáDípò igi, bàbàÀti dípò òkúta, irin;Màá fi àlàáfíà ṣe àwọn alábòójútó rẹ,Màá sì fi òdodo ṣe àwọn tó ń yan iṣẹ́ fún ọ.+ 18  A ò ní gbúròó ìwà ipá mọ́ ní ilẹ̀ rẹ,A ò sì ní gbúròó ìparun àti ìwópalẹ̀ nínú àwọn ààlà rẹ.+ O máa pe àwọn ògiri rẹ ní Ìgbàlà,+ o sì máa pe àwọn ẹnubodè rẹ ní Ìyìn. 19  Oòrùn ò ní jẹ́ ìmọ́lẹ̀ rẹ mọ́ ní ọ̀sán,Ìmọ́lẹ̀ òṣùpá ò sì ní mọ́lẹ̀ fún ọ,Torí Jèhófà máa di ìmọ́lẹ̀ ayérayé fún ọ,+Ọlọ́run rẹ sì máa di ẹwà rẹ.+ 20  Oòrùn rẹ ò ní wọ̀ mọ́,Òṣùpá rẹ ò sì ní wọ̀ọ̀kùn,Torí pé Jèhófà máa di ìmọ́lẹ̀ ayérayé fún ọ,+Àwọn ọjọ́ ọ̀fọ̀ rẹ sì máa dópin.+ 21  Gbogbo èèyàn rẹ máa jẹ́ olódodo;Ilẹ̀ náà máa di tiwọn títí láé. Àwọn ni èéhù ohun tí mo gbìn,Iṣẹ́ ọwọ́ mi,+ ká lè ṣe mí lọ́ṣọ̀ọ́.+ 22  Ẹni tó kéré máa di ẹgbẹ̀rún,Ẹni kékeré sì máa di orílẹ̀-èdè alágbára. Èmi fúnra mi, Jèhófà, máa mú kó yára kánkán ní àkókò rẹ̀.”

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “ìmọ́lẹ̀ àárọ̀ rẹ.”
Ní Héb., “bò ọ́.”
Tàbí “ilé ẹwà mi.”
Tàbí “àlàfo ilé ẹyẹ.”
Tàbí “ṣe ọ́ lọ́ṣọ̀ọ́.”
Tàbí “ló wà bíi ti àkọ́kọ́.”
Tàbí “ìtẹ́wọ́gbà.”