Àìsáyà 46:1-13

  • Àwọn òrìṣà Bábílónì àti Ọlọ́run Ísírẹ́lì (1-13)

    • Jèhófà ń sọ ohun tó máa ṣẹlẹ̀ lọ́jọ́ iwájú (10)

    • Ẹyẹ aṣọdẹ láti ìlà oòrùn (11)

46  Bélì bẹ̀rẹ̀ mọ́lẹ̀,+ Nébò tẹ̀ ba síwájú. Wọ́n kó àwọn òrìṣà wọn sẹ́yìn àwọn ẹranko, sẹ́yìn àwọn ẹran akẹ́rù,+Bí ẹrù tó ń ni àwọn ẹranko tó ti rẹ̀ lára.   Wọ́n jọ tẹ̀ ba, wọ́n sì jọ bẹ̀rẹ̀ mọ́lẹ̀;Wọn ò lè gba àwọn ẹrù* náà sílẹ̀,Àwọn fúnra wọn* sì lọ sí ìgbèkùn.   “Fetí sí mi, ìwọ ilé Jékọ́bù àti gbogbo ẹ̀yin tó ṣẹ́ kù ní ilé Ísírẹ́lì,+Ẹ̀yin tí mò ń tì lẹ́yìn látìgbà tí a ti bí yín, tí mo sì gbé látinú oyún.+   Títí o fi máa dàgbà, mi ò ní yí pa dà;+Títí irun rẹ fi máa funfun, mi ò ní yéé gbé ọ. Bí mo ti ń ṣe, màá gbé ọ, màá rù ọ́, màá sì gbà ọ́ sílẹ̀.+   Ta lẹ lè fi mí wé, tí ẹ lè mú bá mi dọ́gba tàbí tí ẹ lè fi díwọ̀n mi,+Tí a máa wá rí bákan náà?+   Àwọn kan wà tó ń kó wúrà jáde yàlàyòlò látinú àpò wọn;Wọ́n ń wọn fàdákà lórí òṣùwọ̀n. Wọ́n gba oníṣẹ́ irin síṣẹ́, ó sì fi ṣe ọlọ́run.+ Wọ́n wá wólẹ̀, àní, wọ́n jọ́sìn rẹ̀.*+   Wọ́n gbé e sí èjìká wọn,+Wọ́n gbé e, wọ́n sì fi sí àyè rẹ̀, ṣe ló kàn dúró síbẹ̀. Kì í kúrò ní àyè rẹ̀.+ Wọ́n ké sí i, àmọ́ kò dáhùn;Kò lè gba ẹnikẹ́ni nínú wàhálà.+   Ẹ rántí èyí, kí ẹ sì mọ́kàn le. Ẹ fi sọ́kàn, ẹ̀yin ẹlẹ́ṣẹ̀.   Ẹ rántí àwọn nǹkan àtijọ́* tó ti wà tipẹ́,Pé èmi ni Ọlọ́run,* kò sí ẹlòmíì,Èmi ni Ọlọ́run, kò sí ẹni tó dà bí èmi.+ 10  Láti ìbẹ̀rẹ̀, mò ń sọ ohun tó máa ṣẹlẹ̀,Tipẹ́tipẹ́ ni mo sì ti ń sọ àwọn ohun tí kò tíì ṣẹlẹ̀.+ Mo sọ pé, ‘Ìpinnu mi* máa dúró,+Màá sì ṣe ohunkóhun tó bá wù mí.’+ 11  Màá pe ẹyẹ aṣọdẹ wá láti ibi tí oòrùn ti ń yọ,*+Ọkùnrin tó máa ṣe ohun tí mo pinnu*+ máa wá láti ilẹ̀ tó jìn. Mo ti sọ̀rọ̀, màá sì mú kó ṣẹ. Mo ti ní in lọ́kàn, màá sì ṣe é.+ 12  Ẹ fetí sí mi, ẹ̀yin ọlọ́kàn líle,*Ẹ̀yin tí ẹ jìnnà réré sí òdodo. 13  Mo ti mú òdodo mi sún mọ́ tòsí;Kò jìnnà réré,Ìgbàlà mi ò sì ní falẹ̀.+ Màá mú kí wọ́n rí ìgbàlà ní Síónì, ẹwà mi sì máa wà ní Ísírẹ́lì.”+

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Ìyẹn, àwọn òrìṣà tí wọ́n kó sẹ́yìn àwọn ẹranko.
Tàbí “Ọkàn wọn.”
Ní Héb., “forí balẹ̀ fún un.”
Ní Héb., “àkọ́kọ́.”
Tàbí “Olú Ọ̀run.”
Tàbí “Ohun tí mo ní lọ́kàn; Ìmọ̀ràn mi.”
Tàbí “ìlà oòrùn.”
Tàbí “ohun tí mo ní lọ́kàn; ìmọ̀ràn mi.”
Ní Héb., “ọlọ́kàn tó yi.”