Àìsáyà 64:1-12

  • Àdúrà ìrònúpìwàdà ń bá a lọ (1-12)

    • Jèhófà, “Ẹni tó mọ wá” (8)

64  Ká ní o ti fa ọ̀run ya, tí o sì sọ̀ kalẹ̀,Kí àwọn òkè lè mì tìtì nítorí rẹ,   Bí ìgbà tí iná ran igi wíwẹ́,Tí iná sì mú kí omi hó,Àwọn ọ̀tá rẹ máa wá mọ orúkọ rẹ,Àwọn orílẹ̀-èdè sì máa gbọ̀n rìrì níwájú rẹ!   Nígbà tí o ṣe àwọn ohun tó ń bani lẹ́rù, tí a ò jẹ́ retí,+O sọ̀ kalẹ̀, àwọn òkè sì mì tìtì níwájú rẹ.+   Láti ìgbà àtijọ́, kò sẹ́ni tó gbọ́ tàbí tó fetí sílẹ̀,Kò sí ojú tó rí Ọlọ́run kankan àfi ìwọ,Tó ń gbé ìgbésẹ̀ nítorí àwọn tó ń retí rẹ̀.*+   O ti bá àwọn tó ń fayọ̀ ṣe ohun tó tọ́ pàdé,+Àwọn tó ń rántí rẹ, tí wọ́n sì ń tẹ̀ lé àwọn ọ̀nà rẹ. Wò ó! Inú bí ọ, nígbà tí à ń ṣẹ̀ ṣáá,+Ó pẹ́ gan-an tí a fi ṣe bẹ́ẹ̀. Ṣé ó wá yẹ ká rígbàlà báyìí?   Gbogbo wa ti dà bí aláìmọ́,Gbogbo iṣẹ́ òdodo wa sì dà bí aṣọ tí wọ́n fi ṣe nǹkan oṣù.+ Gbogbo wa máa rọ bí ewé,Àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa sì máa gbé wa lọ bí atẹ́gùn.   Kò sẹ́ni tó ń pe orúkọ rẹ,Kò sẹ́ni tó ń ru ara rẹ̀ sókè láti gbá ọ mú,Torí o ti fi ojú rẹ pa mọ́ fún wa,+O sì mú ká ṣègbé* torí* ẹ̀ṣẹ̀ wa.   Àmọ́ ní báyìí, Jèhófà, ìwọ ni Bàbá wa.+ Àwa ni amọ̀, ìwọ sì ni Ẹni tó mọ wá;*+Iṣẹ́ ọwọ́ rẹ ni gbogbo wa.   Jèhófà, má ṣe bínú jù,+Má sì rántí àwọn àṣìṣe wa títí láé. Jọ̀ọ́, wò wá, torí èèyàn rẹ ni gbogbo wa. 10  Àwọn ìlú mímọ́ rẹ ti di aginjù. Síónì ti di aginjù,Jerúsálẹ́mù ti di ahoro.+ 11  Ilé* wa mímọ́ àti ológo,*Tí àwọn baba ńlá wa ti yìn ọ́,Ni wọ́n ti dáná sun,+Gbogbo àwọn ohun tó ṣeyebíye sí wa sì ti pa run. 12  Pẹ̀lú èyí, ṣé o ṣì máa dúró, Jèhófà? Ṣé o ṣì máa dákẹ́ jẹ́ẹ́, tí wàá sì jẹ́ kí ìyà jẹ wá gidigidi?+

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “tó ń fi sùúrù dúró dè é.”
Ní Héb., “látọwọ́.”
Ní Héb., “yọ́.”
Tàbí “Ẹni tó dá wa; Amọ̀kòkò.”
Tàbí “Tẹ́ńpìlì.”
Tàbí “ẹlẹ́wà.”