Àìsáyà 13:1-22

  • Ọ̀rọ̀ ìkéde sí Bábílónì (1-22)

    • Ọjọ́ Jèhófà sún mọ́lé! (6)

    • Àwọn ará Mídíà máa ṣẹ́gun Bábílónì (17)

    • Wọn ò ní gbé inú Bábílónì mọ́ láé (20)

13  Ọ̀rọ̀ ìkéde sí Bábílónì,+ tí Àìsáyà+ ọmọ Émọ́ọ̀sì rí nínú ìran:   “Ẹ gbé àmì kan*+ sókè lórí òkè tó jẹ́ kìkì àpáta. Ẹ ké pè wọ́n, ẹ ju ọwọ́,Kí wọ́n lè wá sí ẹnu ọ̀nà àwọn èèyàn pàtàkì.   Mo ti pàṣẹ fún àwọn tí mo yàn.*+ Mo ti ké sí àwọn jagunjagun mi pé kí wọ́n fi ìbínú mi hàn,Àwọn èèyàn mi tó ń yangàn, tí wọ́n sì ń yọ̀.   Fetí sílẹ̀! Ọ̀pọ̀ èèyàn wà lórí òkè;Ìró wọn dà bí ìró ọ̀pọ̀ rẹpẹtẹ èèyàn! Fetí sílẹ̀! Ariwo àwọn ìjọba,Ti àwọn orílẹ̀-èdè tó kóra jọ!+ Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun ń pe àwọn ọmọ ogun jọ.+   Wọ́n ń bọ̀ láti ilẹ̀ tó jìnnà,+Láti ìkángun ọ̀run,Jèhófà àti àwọn ohun ìjà ìbínú rẹ̀,Láti pa gbogbo ayé run.+   Ẹ pohùn réré ẹkún, torí ọjọ́ Jèhófà sún mọ́lé! Ó máa jẹ́ ọjọ́ ìparun látọ̀dọ̀ Olódùmarè.+   Ìdí nìyẹn tí gbogbo ọwọ́ fi máa rọ,Tí ìbẹ̀rù sì máa mú kí ọkàn gbogbo èèyàn domi.+   Jìnnìjìnnì bo àwọn èèyàn náà.+ Iṣan wọn sún kì, wọ́n sì ń jẹ̀rora,Bí obìnrin tó ń rọbí. Wọ́n ń wo ara wọn tìbẹ̀rù-tìbẹ̀rù,Ìrora sì hàn lójú wọn.   Wò ó! Ọjọ́ Jèhófà ń bọ̀,Ọjọ́ tó lágbára pẹ̀lú ìbínú tó le àti ìbínú tó ń jó fòfò,Láti sọ ilẹ̀ náà di ohun àríbẹ̀rù,+Kó sì pa àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ilẹ̀ náà run kúrò lórí rẹ̀. 10  Torí àwọn ìràwọ̀ ojú ọ̀run àti àwọn àgbájọ ìràwọ̀ wọn*+Kò ní tan ìmọ́lẹ̀ wọn jáde;Oòrùn máa ṣókùnkùn tó bá ràn,Òṣùpá ò sì ní tan ìmọ́lẹ̀ rẹ̀. 11  Màá pe àwọn tó ń gbé ayé lẹ́jọ́ torí ìwà burúkú wọn,+Màá sì pe àwọn ẹni burúkú lẹ́jọ́ torí ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Màá fòpin sí ìyangàn àwọn agbéraga,Màá sì rẹ ìgbéraga àwọn oníwà ìkà wálẹ̀.+ 12  Màá mú kí ẹni kíkú ṣọ̀wọ́n ju wúrà tí wọ́n yọ́ mọ́,+Màá sì mú kí àwọn èèyàn ṣọ̀wọ́n ju wúrà Ófírì.+ 13  Ìdí nìyẹn tí màá fi mú kí ọ̀run gbọ̀n rìrì,Ayé sì máa mì jìgìjìgì kúrò ní àyè rẹ̀+Nígbà tí Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun bá bínú gidigidi ní ọjọ́ ìbínú rẹ̀ tó ń jó bí iná. 14  Bí egbin tí wọ́n ń dọdẹ àti bí agbo ẹran tí kò sí ẹnikẹ́ni tó máa kó wọn jọ,Kálukú máa pa dà sọ́dọ̀ àwọn èèyàn rẹ̀;Kálukú sì máa sá lọ sí ilẹ̀ rẹ̀.+ 15  Wọ́n máa gún ẹnikẹ́ni tí wọ́n bá rí ní àgúnyọ,Wọ́n sì máa fi idà pa ẹnikẹ́ni tí wọ́n bá mú.+ 16  Wọ́n máa já àwọn ọmọ wọn sí wẹ́wẹ́ níṣojú wọn,+Wọ́n máa kó ẹrù ilé wọn,Wọ́n sì máa fipá bá àwọn ìyàwó wọn lò pọ̀. 17  Màá gbé àwọn ará Mídíà dìde sí wọn,+Àwọn tí kò ka fàdákà sí nǹkan kan,Tí wúrà ò sì já mọ́ nǹkan kan lójú wọn. 18  Ọfà wọn máa run àwọn ọ̀dọ́kùnrin túútúú;+Wọn ò ní káàánú èso ikùn,Wọn ò sì ní ṣàánú àwọn ọmọdé. 19  Bábílónì tó lógo* jù nínú àwọn ìjọba,+Ẹwà àti ògo àwọn ará Kálídíà,+Máa dà bíi Sódómù àti Gòmórà nígbà tí Ọlọ́run bì wọ́n ṣubú.+ 20  Ẹnikẹ́ni ò ní gbé inú rẹ̀ mọ́ láé,Kò sì sẹ́ni tó máa gbé ibẹ̀ láti ìran dé ìran.+ Ará Arébíà kankan ò ní pàgọ́ síbẹ̀,Olùṣọ́ àgùntàn kankan ò sì ní jẹ́ kí agbo ẹran rẹ̀ sinmi níbẹ̀. 21  Àwọn ẹranko inú aṣálẹ̀ máa dùbúlẹ̀ síbẹ̀;Àwọn ẹyẹ òwìwí máa kún ilé wọn. Àwọn ògòǹgò á máa gbé ibẹ̀,+Àwọn ewúrẹ́ igbó* á máa tọ kiri níbẹ̀. 22  Àwọn ẹranko tó ń hu á máa ké nínú àwọn ilé gogoro rẹ̀Àti àwọn ajáko* nínú àwọn ààfin rẹ̀ tó lọ́lá. Àkókò rẹ̀ ti sún mọ́lé, a ò sì ní fi kún àwọn ọjọ́ rẹ̀.”+

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “òpó kan láti fi ṣe àmì.”
Ní Héb., “tí mo sọ di mímọ́.”
Ní Héb., “àti àwọn Késílì wọn,” ó ṣeé ṣe kó jẹ́ Óríónì àtàwọn àgbájọ ìràwọ̀ tó yí i ká ló ń tọ́ka sí.
Tàbí “lọ́ṣọ̀ọ́.”
Tàbí kó jẹ́, “Àwọn ẹ̀mí èṣù tó rí bí ewúrẹ́.”
Tàbí “akátá.”