Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN | JÓẸ́LÌ 1-3

‘Àwọn Ọmọkùnrin Yín àti Àwọn Ọmọbìnrin Yín Yóò Máa Sọ Tẹ́lẹ̀’

‘Àwọn Ọmọkùnrin Yín àti Àwọn Ọmọbìnrin Yín Yóò Máa Sọ Tẹ́lẹ̀’

2:28, 29

Àwọn Kristẹni ẹni àmì òróró ń kópa nínú iṣẹ́ ìsọtẹ́lẹ̀. Wọ́n ń sọ̀rọ̀ nípa “àwọn ohun ọlá ńlá Ọlọ́run” wọ́n sì ń kéde “ìhìn rere ìjọba” náà. (Iṣe 2:​11, 17-21; Mt 24:14) Àwọn àgùntàn mìíràn ń tì wọ́n lẹ́yìn lẹ́nu iṣẹ́ yìí

2:32

Kí ló túmọ̀ sí láti “ké pe orúkọ Jèhófà”?

  • Ká mọ orúkọ rẹ̀

  • Ká bọ̀wọ̀ fún orúkọ rẹ̀

  • Ká gbára lé Ẹni tó ń jẹ́ orúkọ náà ká sì gbẹ́kẹ̀ lé e

Bi ara rẹ pé, ‘Báwo ni mo ṣe lè ti àwọn ẹni àmì òróró lẹ́yìn lẹ́nu iṣẹ́ ìsọtẹ́lẹ̀?’