Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

ÀPÓTÍ Ẹ̀KỌ́ 16B

Ìgbà Wo Ni Ìkẹ́dùn, Ìkérora, Ìsàmì àti Fífọ́ Nǹkan Máa Ṣẹlẹ̀, Báwo Ló sì Ṣe Máa Ṣẹlẹ̀?

Ìgbà Wo Ni Ìkẹ́dùn, Ìkérora, Ìsàmì àti Fífọ́ Nǹkan Máa Ṣẹlẹ̀, Báwo Ló sì Ṣe Máa Ṣẹlẹ̀?

Ìran tó wà lákọọ́lẹ̀ nínú ìwé Ìsíkíẹ́lì orí 9 ń ṣẹ lóde òní. Òye tá a bá ní nípa bí àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ náà ṣe máa wáyé lè fi wá lọ́kàn balẹ̀ bí òpin ètò àwọn nǹkan yìí ṣe ń sún mọ́lé

‘Wọ́n ń kẹ́dùn, wọ́n sì ń kérora’

ÌGBÀ WO: Láwọn ọjọ́ ìkẹyìn, ṣáájú ìpọ́njú ńlá

BÁWO LÓ ṢE MÁA ṢẸLẸ̀: Àwọn èèyàn tó jẹ́ olóòótọ́ ọkàn ń fi hàn nípa ọ̀rọ̀ àti ìwà wọn pé àwọn ò fara mọ́ ìwàkiwà tó kúnnú ayé yìí. Irú àwọn ẹni bẹ́ẹ̀ tẹ́tí gbọ́ ìwàásù, wọ́n ṣe ohun tó yẹ, wọ́n ń fi àwọn ànímọ́ Kristi ṣèwà hù, wọ́n ṣèrìbọmi láti fi hàn pé wọ́n ti yara wọn sí mímọ́ fún Jèhófà, wọ́n sì jẹ́ adúróṣinṣin sí àwọn arákùnrin Kristi

‘Ìsàmì’

ÌGBÀ WO: Nígbà ìpọ́njú ńlá

BÁWO LÓ ṢE MÁA ṢẸLẸ̀: Ọkùnrin tó ní ìwo yíǹkì akọ̀wé ṣàpẹẹrẹ Jésù Kristi nígbà tó bá dé gẹ́gẹ́ bí Onídàájọ́ gbogbo orílẹ̀-èdè. Ó máa dá ogunlọ́gọ̀ èèyàn láre, lédè míì, ó máa sàmì sí wọn pé wọ́n jẹ́ àgùntàn, ìyẹn fi hàn pé wọ́n á la Amágẹ́dọ́nì já

‘Fífọ́ nǹkan’

ÌGBÀ WO: Ní Amágẹ́dọ́nì

BÁWO LÓ ṢE MÁA ṢẸLẸ̀: Jésù Kristi àtàwọn ọmọ ogun ọ̀run, ìyẹn àwọn áńgẹ́lì àtàwọn ọ̀kẹ́ méje ó lé ẹgbàajì (144,000) tí wọ́n ń jọba pẹ̀lú Jésù, máa pa ayé búburú yìí run pátápátá, wọ́n á sì gba àwọn tó ń ṣe ìjọsìn mímọ́ là sínú ayé tuntun