Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

ORIN 69

Máa Wàásù Ìjọba Náà

Máa Wàásù Ìjọba Náà

(2 Tímótì 4:5)

  1. 1. Ẹ tẹ̀ síwájú, ẹ máa wàásù.

    Ẹ kéde orúkọ Jáà.

    Ẹ wá àwọn onírẹ̀lẹ̀ lọ

    Torí ‘fẹ́ tẹ́ ẹ ní sí wọn.

    Àǹfààní aláìlẹ́gbẹ́ ló jẹ́

    Láti bá Ọlọ́run ṣiṣẹ́.

    Torí náà, ká máa fayọ̀ wàásù;

    Ká kéde òótọ́ fáráyé.

    (ÈGBÈ)

    Tẹ̀ síwájú, fìgboyà wàásù

    ‘Jọba náà fáráyé.

    Tẹ̀ síwájú, kó o jẹ́ adúróṣinṣin

    sí Jèhófà.

  2. 2. Àwọn ẹni àmì òróró

    Àti àgùntàn mìíràn;

    Gbogbo wa lọ́kùnrin, lóbìnrin

    Ni ká máa tẹ̀ síwájú.

    Ó yẹ kí gbogbo ayé gbọ́ pé

    Ìjọba Ọlọ́run dé tán.

    Bá a ṣe ń wàásù, ẹ̀rù kìí bà wá.

    Jèhófà ló wà lẹ́yìn wa.

    (ÈGBÈ)

    Tẹ̀ síwájú, fìgboyà wàásù

    ‘Jọba náà fáráyé.

    Tẹ̀ síwájú, kó o jẹ́ adúróṣinṣin

    sí Jèhófà.