Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

ORIN 65

Ẹ Tẹ̀ Síwájú!

Ẹ Tẹ̀ Síwájú!

(Hébérù 6:1)

  1. 1. Ẹ máa tẹ̀ síwájú, nínú òtítọ́.

    Ká tan ìmọ́lẹ̀ òótọ́ fún gbogbo aráyé.

    Jẹ́ kíṣẹ́ òjíṣẹ́ rẹ máa sunwọ̀n sí i;

    Kó o gbẹ́kẹ̀ lé Ọlọ́run.

    Gbogbo wa ló yẹ ká ṣiṣẹ́ yìí.

    Rántí pé Jésù náà ṣiṣẹ́ yìí.

    Máa bẹ Ọlọ́run pé kó dúró tì ọ́,

    Kó o lè jẹ́ olódodo.

  2. 2. Ẹ máa tẹ̀ síwájú, fìgboyà wàásù.

    Ká sọ ìròyìn ayọ̀ fún gbogbo aráyé.

    Ẹ jẹ́ ká máa wàásù látilé délé,

    Ká fi yin Jáà, Ọba wa.

    Báwọn ọ̀tá tiẹ̀ ń halẹ̀ mọ́ wa,

    Má bẹ̀rù, ṣáà máa fòótọ́ kọ́ni.

    Ká jẹ́ kí gbogbo èèyàn mọ̀ pé láìpẹ́,

    ’Jọba Ọlọ́run máa dé.

  3. 3. Ẹ máa tẹ̀ síwájú, ẹ má ṣe yẹsẹ̀.

    Ká sì máa sunwọ̀n sí i,

    Iṣẹ́ ṣì pọ̀ láti ṣe.

    Jẹ́ kí ẹ̀mí Ọlọ́run máa darí rẹ,

    Yóò sì máa fún ọ láyọ̀.

    Nífẹ̀ẹ́ àwọn tí ò ń kọ́ lẹ́kọ̀ọ́.

    Kọ́ wọn kí òótọ́ lè dọ́kàn wọn.

    Ràn wọ́n lọ́wọ́ kí wọ́n lè dàgbà dénú,

    Kí ‘mọ́lẹ̀ òótọ́ lè tàn.