Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

ORIN 139

Fojú Inú Wo Ìgbà Tí Gbogbo Nǹkan Máa Di Tuntun

Fojú Inú Wo Ìgbà Tí Gbogbo Nǹkan Máa Di Tuntun

(Ìfihàn 21:1-5)

  1. 1. Wo ara rẹ àtèmi náà

    Bíi pé a wà nínú ayé tuntun.

    Wo bí yóò ṣe rí lára rẹ

    Pé gbogbo ayé wà lálàáfíà.

    Kò sí èèyàn búburú mọ́;

    Ìjọba Ọlọ́run dúró láé.

    Àkókò ìtura ti dé fáráyé

    A ó máa kọrin ìyìn jáde

    látọkàn wá:

    (ÈGBÈ)

    “A dúpẹ́, Jèhófà Ọlọ́run wa.

    Ìjọba Ọmọ rẹ sọ nǹkan dọ̀tun.

    Ayọ̀ kún ọkàn wa, a sì ń kọrin ọpẹ́.

    Kí ògo, ìyìn àtọlá jẹ́ tìrẹ láé.”

  2. 2. Wo ara rẹ, wo èmi náà,

    Bá ó ṣe jọ máa gbádùn láyé tuntun.

    Ìbànújẹ́ kò ní sí mọ́;

    Kò sóhun tó máa dẹ́rù bà wá.

    Ìlérí Ọlọ́run máa ṣẹ:

    Àgọ́ rẹ̀ yóò bo gbogbo ayé.

    Yóò sì jí àwọn tó ń sùn nínú ikú;

    Àwọn àtàwa náà yóò máa

    kọrin ọpẹ́:

    (ÈGBÈ)

    “A dúpẹ́, Jèhófà Ọlọ́run wa.

    Ìjọba Ọmọ rẹ sọ nǹkan dọ̀tun.

    Ayọ̀ kún ọkàn wa, a sì ń kọrin ọpẹ́.

    Kí ògo, ìyìn àtọlá jẹ́ tìrẹ láé.”