Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Òye Jésù Ṣe Àwọn Tó Gbọ́rọ̀ Rẹ̀ Ní Kàyéfì

Òye Jésù Ṣe Àwọn Tó Gbọ́rọ̀ Rẹ̀ Ní Kàyéfì

Abala Àwọn Ọ̀dọ́

Òye Jésù Ṣe Àwọn Tó Gbọ́rọ̀ Rẹ̀ Ní Kàyéfì

Ohun tó o máa ṣe: Ibi tí kò sáriwo ni kó o ti ṣe ìdánrawò yìí. Bó o ṣe ń ka àwọn ẹsẹ Ìwé Mímọ́ tó wà nísàlẹ̀ yìí, máa fojú inú wò ó pé o wà níbi tí ohun tó ò ń kà náà ti ṣẹlẹ̀, kó dà bíi pé ò ń gbọ́ báwọn èèyàn náà ṣe ń sọ̀rọ̀. Kó o sì máa fojú inú wò ó bí ohun tó ń ṣẹlẹ̀ lọ́wọ́lọ́wọ́.

KA ÌTÀN NÁÀ DÁADÁA.KA LÚÙKÙ 2:41-47.

Tó o bá fojú inú wo ohun tí ẹsẹ kẹrìndínláàádọ́ta sọ, ọ̀rọ̀ kí lo rò pé Jésù àtàwọn olùkọ́ yẹn jọ ń sọ?

․․․․․

ṢÈWÁDÌÍ KÓ O SÌ RONÚ JINLẸ̀.

Kí lo rò pé ó jẹ́ kí Jésù lè bá àwọn olórí ẹ̀sìn yẹn sọ̀rọ̀ pa pọ̀ bó ṣe jẹ́ ọmọdé tó yẹn? Ṣé torí pé ó jẹ́ ẹni pípé ni, àbí ó tún nídìí míì tó fi rí bẹ́ẹ̀?

․․․․․

KA ÌTÀN NÁÀ DÁADÁA.KA LÚÙKÙ 2:48-52.

Irú ìwà wo lo rò pé Jésù hù sáwọn òbí ẹ̀ nígbà tó béèrè lọ́wọ́ wọn pé: “Èé ṣe tí ẹ fi ní láti máa wá mi?”

․․․․․

Kí ló mú kó dá wa lójú pé Jésù kò fìbínú sọ̀rọ̀ sáwọn òbí ẹ̀ àti pé ó bọ̀wọ̀ fún wọn?

․․․․․

ṢÈWÁDÌÍ KÓ O SÌ RONÚ JINLẸ̀.

Kí nìdí tá a fi gbà pé Jósẹ́fù àti Màríà máa dààmú lóòótọ́?

․․․․․

Bó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹni pípé ni Jésù, kí nìdí tó fi ń bá a lọ láti máa gbọ́ràn sáwọn òbí rẹ̀ lẹ́nu?

․․․․․

Ǹjẹ́ o ronú pé ó ṣeé ṣe kí ojú ti Jésù bí àwọn òbí rẹ̀ ṣe bá a wí lójú àwọn èèyàn tó fẹ́ràn rẹ̀?

․․․․․

MÁA FOHUN TÓ O KỌ́ ṢÈWÀ HÙ. ṢÀKỌSÍLẸ̀ Ẹ̀KỌ́ TÓ O KỌ́ NÍPA . . .

Jíjẹ́ ẹni tó ń tẹrí ba.

․․․․․

Bó ti ṣe pàtàkì tó pé kéèyàn kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì nígbà tó wà lọ́mọdé.

․․․․․

KÍ LÓ WÚ Ẹ LÓRÍ JÙ NÍNÚ ÌTÀN INÚ BÍBÉLÌ YÌÍ, KÍ SÌ NÌDÍ?

․․․․․