Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Bí Sódómù àti Gòmórà Ṣe Pa Run

Bí Sódómù àti Gòmórà Ṣe Pa Run

Abala Àwọn Ọ̀dọ́

Bí Sódómù àti Gòmórà Ṣe Pa Run

Ohun tó o máa ṣe: Ibi tí kò sáriwo ni kó o ti ṣe ìdánrawò yìí. Bó o ṣe ń ka àwọn ẹsẹ Ìwé Mímọ́ tó wà nísàlẹ̀ yìí, máa fojú inú wò ó pé o wà níbi tí ohun tó ò ń kà náà ti ṣẹlẹ̀, kó dà bíi pé ò ń gbọ́ báwọn èèyàn náà ṣe ń sọ̀rọ̀. Kó o sì máa fojú inú wo bí nǹkan ṣe rí lára àwọn tó kópa pàtàkì nínú ìṣẹ̀lẹ̀ náà.

KA ÌTÀN NÁÀ DÁADÁA.KA JẸ́NẸ́SÍSÌ 19:1-14.

Bó o ṣe ń finú yàwòrán àwọn àlejò Lọ́ọ̀tì, sọ bí wọ́n ṣe rí.

․․․․․

Àwọn wo ló wà nínú àwọn ewèlè èèyàn yẹn?

․․․․․

ṢÈWÁDÌÍ KÓ O SÌ RONÚ JINLẸ̀.—KA JẸ́NẸ́SÍSÌ 13:7-13.

Báwo ni Lọ́ọ̀tì ṣe dẹni tó ń gbé ní ìlú Sódómù?

․․․․․

Kí nìdí tí Jèhófà fi sọ pé òun yóò pa àwọn tó ń gbé ìlú náà run?

․․․․․

KA JẸ́NẸ́SÍSÌ 19:15-26.

Báwo ni Jèhófà ṣe gba ti Lọ́ọ̀tì rò?

․․․․․

Kí ló mú kí aya Lọ́ọ̀tì bojú wẹ̀yìn?

․․․․․

Kí ló ṣekú pa aya Lọ́ọ̀tì?

․․․․․

MÁA FOHUN TÓ O KỌ́ ṢÈWÀ HÙ. ṢÀKỌSÍLẸ̀ Ẹ̀KỌ́ TÓ O KỌ́ NÍPA . . .

Ojú tí Jèhófà fi ń wo ìwà ibi.

․․․․․

Bí Jèhófà ṣe jẹ́ aláàánú.

․․․․․

Bí Jèhófà ṣe kọ́kọ́ máa ń kìlọ̀ fáwọn èèyàn rẹ̀ kó tó ṣèdájọ́ wọn.

․․․․․

Apá wo ló gbàfiyèsí rẹ jù lọ nínú ìtàn yìí, kí sì nìdí?

․․․․․

․․․․․