Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

“Kí Ìjọba Rẹ Dé”​—Àdúrà Tí Àìmọye Èèyàn Ń Gbà

“Kí Ìjọba Rẹ Dé”​—Àdúrà Tí Àìmọye Èèyàn Ń Gbà

Ṣé o ti gbàdúrà rí pé kí Ìjọba Ọlọ́run dé? Àìmọye ọdún làwọn èèyàn ti fi gbàdúrà pé “Kí ìjọba rẹ dé.” Kí nìdí tí wọ́n fi ń gbàdúrà yẹn? Ìdí ni pé Jésù sọ fáwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ pé kí wọ́n máa gbàdúrà pé kí Ìjọba Ọlọ́run dé.

Gbogbo ohun tí Jésù sọ nípa Ìjọba náà kò kọ́kọ́ yé àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀. Ìgbà kan wà tí wọ́n béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé: “Olúwa, ṣé àkókò yìí lo máa dá ìjọba pa dà fún Ísírẹ́lì?” Ó ṣeé ṣe kó yà wọ́n lẹ́nu pé Jésù kò dáhùn ìbéèrè wọn ní tààràtà. (Ìṣe 1:6, 7) Ṣé a lè mọ ohun tí Ìjọba Ọlọ́run jẹ́ àti ìgbà tó máa dé? Bẹ́ẹ̀ ni, a lè mọ̀ ọ́n!

Ìwé yìí máa jẹ́ kó o mọ ìdáhùn àwọn ìbéèrè yìí:

  • Kí nìdí tá a fi nílò Ìjọba Ọlọ́run?

  • Ta ni Ọba Ìjọba Ọlọ́run?

  • Ìgbà wo ni Ìjọba Ọlọ́run máa bẹ̀rẹ̀ sí í ṣàkóso ayé? 

  • Kí ni Ìjọba Ọlọ́run máa ṣe?

  • Kí nìdí tó fi yẹ kó o fara mọ́ Ìjọba Ọlọ́run nísinsìnyí?

  • Kí ni Ìjọba Ọlọ́run?