Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Kí Ni Ìdáhùn Rẹ?

Kí Ni Ìdáhùn Rẹ?

Kí Ni Ìdáhùn Rẹ?

Kí Ni Kò Tọ̀nà Nínú Àwòrán Yìí?

Tọ́ka sí ohun mẹ́ta nínú àwòrán yìí tó yàtọ̀ sí ohun tó wà nínú Jẹ́nẹ́sísì 7:1-9, 13-16, 23; 8:15-19.

1. ․․․․․

2. ․․․․․

AMỌ̀NÀ: Wo Léfítíkù 11:3 àti Diutarónómì 14:4.

3. ․․․․․

AMỌ̀NÀ: Wo Diutarónómì 14: 7-19.

FÚN ÌJÍRÒRÒ: Báwo làwọn ọmọ Nóà àtàwọn ìyàwó wọn ṣe ràn án lọ́wọ́? Báwo lo ṣe lè tẹ̀ lé àpẹẹrẹ àwọn ọmọ Nóà?

Nínú Ìtẹ̀jáde Yìí

Dáhùn àwọn ìbéèrè yìí, kó o sì kọ (àwọn) ẹsẹ Bíbélì tó yẹ sínú àlàfo.

OJÚ ÌWÉ 6 Kí lẹni tó fẹ́ràn owó ò ní ní? Oníwàásù 5:․․․

OJÚ ÌWÉ 9 Àwọn wo ló máa láyọ̀? Mátíù 5:․․․

OJÚ ÌWÉ 18 Kí ni kò yẹ kéèyàn ṣe bó bá ń gbàdúrà? Mátíù 6:․․․

OJÚ ÌWÉ 28 Kí ló yẹ ká ṣe nípa àwọn àníyàn wa? 1 Pétérù 5:․․․

Àwọn Wo Ló Wà Lára Ìdílé Jésù?

Kọ́kọ́ wo ohun tá a kọ sínú amọ̀nà. Ka ẹsẹ Ìwé Mímọ́ tá a tọ́ka sí. Lẹ́yìn náà, kọ orúkọ tó tọ̀nà sínú àlàfo.

4. ․․․․․

AMỌ̀NÀ: Bó tilẹ̀ jẹ́ pé àpẹẹrẹ burúkú ni bàbá mi fi lélẹ̀, síbẹ̀ mo jẹ́ ọba tó ń “bá a nìṣó ní fífà mọ́ Jèhófà.”

Ka 2 Àwọn Ọba 18:1-6.

5. ․․․․․

AMỌ̀NÀ: Mo ṣi agbára mi lò nípa títa ẹ̀jẹ̀ àwọn aláìmọwọ́-mẹsẹ̀ sílẹ̀ ní ìwọ̀n púpọ̀ gidigidi.

Ka 2 Àwọn Ọba 21:16.

6. ․․․․․

AMỌ̀NÀ: Mo tẹ̀ lé àpẹẹrẹ burúkú tí bàbá mi fi lélẹ̀, àwọn ìránṣẹ́ mi sì pa mí.

Ka 2 Àwọn Ọba 21:19-23.

ÌDÁHÙN ÀWỌN ÌBÉÈRÈ

1. Ọkọ̀ áàkì ò ní irú iwájú àti ẹ̀yìn tí ọkọ̀ ojú omi máa ń ní.

2. Nóà mú méje nínú àwọn ẹranko tí ó “mọ́,” irú bí àgùntàn, sínú áàkì.

3. Nóà mú onírúurú ẹranko tí “kò mọ́” ní méjì-méjì sínú ọkọ̀ áàkì.

4. Hesekáyà.—Mátíù 1:9.

5. Mánásè.—Mátíù 1:10.

6. Ámọ́nì.—Mátíù 1:10.