MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI
Àǹfààní Tá A Ní Láti Kọ́ Àwọn Ibi Tí A Ti Ń Ṣe Ìjọsìn Tòótọ́ Ká sì Máa Bójú Tó Wọn
Ó gba ọ̀pọ̀ ìsapá àti ìnáwó kí wọ́n tó lè kọ́ Tẹ́ńpìlì ní Ísírẹ́lì. Síbẹ̀, àwọn ọmọ Ísírẹ́lì fi ìtara kọ́wọ́ ti iṣẹ́ ìkọ́lé náà. (1Kr 29:
ARA OHUN TÁ A LÈ ṢE NI PÉ . . .
-
Ká máa tún àwọn ibi tá a bá lò tàbí jókòó sí nípàdé ṣe ká tó lọ sílé. Tí a kò bá ní lè ṣe bẹ́ẹ̀ torí àwọn ìdí kan, ká rí i dájú pé àyíká ibi tá a jókòó sí wà ní mímọ́ tónítóní.
-
Ká máa kópa nínú iṣẹ́ ìmọ́tótó àti àtúnṣe Gbọ̀ngàn Ìjọba tá a máa ń ṣe déédéé. Àgbájọ ọwọ́ la fi ń sọ̀yà, tá a bá ń pawọ́ pọ̀ ṣe é, iṣẹ́ náà á dínkù, ayọ̀ wa á sì kún.
—lv ojú ìwé 92 àti 93 ìpínrọ̀ 18. -
Ká máa fowó ṣètìlẹyìn. Kódà, inú Jèhófà dùn sí ìtìlẹ́yìn tó tọkàn wá tó dà bí ‘ẹyọ owó kéékèèké méjì tí ìníyelórí wọ́n kéré gan-an’ tá a bá fún un.
—Mk 12: 41-44. -
Ká máa yọ̀ǹda ara wa tí ipò wa bá gbà bẹ́ẹ̀ láti máa kọ́ àwọn ilé tí ètò Ọlọ́run ń lò, ká sì máa ṣàtúnṣe wọn. Kì í ṣe dandan ká ti nírìírí lẹ́nu iṣẹ́ ìkọ́lé ká tó lè yọ̀ǹda ara wa fún iṣẹ́ yìí.