Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

ORIN 26

Ẹ Ti Ṣe É fún Mi

Ẹ Ti Ṣe É fún Mi

(Mátíù 25:34-40)

  1. 1. Àwọn arákùnrin Kristi tó wà láyé

    ni àwọn àgùntàn mìíràn ńbá ṣiṣẹ́.

    Gbogbo ìsapá wọn

    láti ràn wọ́n lọ́wọ́

    Ni Jésù sọ pé wọ́n máa gba èrè rẹ̀.

    (ÈGBÈ)

    “Tẹ́ ẹ bá tù wọ́n nínú, ẹ tù mí nínú.

    Ohun tẹ́ ẹ ṣe fún wọn, èmi lẹ ṣe é fún.

    Iṣẹ́ tẹ́ ẹ ṣe fún wọn, èmi lẹ ṣe é fún.

    Bẹ́ ẹ ṣe ṣe é fún wọn, èmi lẹ ṣe é fún.

    Tẹ́ ẹ bá ti ṣe é fún wọn, ẹ ti ṣe é fún mi.”

  2. 2. “Nígbà tébi ń pa mí, tí òùngbẹ sì ń gbẹ mí,

    gbogbo ohun tí mo nílò lẹ pèsè.”

    Wọ́n béèrè pé: “Ìgbà wo

    la ṣe nǹkan wọ̀nyí?”

    Ọba náà máa dá wọn lóhùn, yóò sọ pé:

    (ÈGBÈ)

    “Tẹ́ ẹ bá tù wọ́n nínú, ẹ tù mí nínú.

    Ohun tẹ́ ẹ ṣe fún wọn, èmi lẹ ṣe é fún.

    Iṣẹ́ tẹ́ ẹ ṣe fún wọn, èmi lẹ ṣe é fún.

    Bẹ́ ẹ ṣe ṣe é fún wọn, èmi lẹ ṣe é fún.

    Tẹ́ ẹ bá ti ṣe é fún wọn, ẹ ti ṣe é fún mi.”

  3. 3. “Ẹ ti dúró tì mí, iṣẹ́ rere lẹ̀ ń ṣe.

    Ẹ̀ ń wàásù pẹ̀l’áwọn arákùnrin mi.”

    Ọba máa sọ fáwọn

    tó wà lọ́tùn-ún rẹ̀ pé:

    “Ẹ di pípé, kí ẹ sì jogún ayé.”

    (ÈGBÈ)

    “Tẹ́ ẹ bá tù wọ́n nínú, ẹ tù mí nínú.

    Ohun tẹ́ ẹ ṣe fún wọn, èmi lẹ ṣe é fún.

    Iṣẹ́ tẹ́ ẹ ṣe fún wọn, èmi lẹ ṣe é fún.

    Bẹ́ ẹ ṣe ṣe é fún wọn, èmi lẹ ṣe é fún.

    Tẹ́ ẹ bá ti ṣe é fún wọn, ẹ ti ṣe é fún mi.”