Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

ORIN 21

Ẹ Máa Wá Ìjọba Ọlọ́run Lákọ̀ọ́kọ́

Ẹ Máa Wá Ìjọba Ọlọ́run Lákọ̀ọ́kọ́

(Mátíù 6:33)

  1. 1. Ohun kan tó ṣeyebíye,

    Tó ń mú Jèhófà láyọ̀,

    Ni Ìjọba Jésù Kristi

    Tó máa mú ìfẹ́ Rẹ̀ ṣẹ.

    (ÈGBÈ)

    Ẹ kọ́kọ́ wá Ìjọba náà

    Àtòdodo Jèhófà.

    Ká pòkìkí rẹ̀ fáráyé,

    Ká sì máa fòtítọ́ sìn ín.

  2. 2. Má jẹ́ k’áníyàn rẹ pọ̀ jù;

    ‘Kí la máa jẹ, kí la ó mu?’

    Jèhófà máa pèsè fún wa,

    Ká fi tirẹ̀ sákọ̀ọ́kọ́.

    (ÈGBÈ)

    Ẹ kọ́kọ́ wá Ìjọba náà

    Àtòdodo Jèhófà.

    Ká pòkìkí rẹ̀ fáráyé,

    Ká sì máa fòtítọ́ sìn ín.

  3. 3. Ká wàásù ìhìnrere náà.

    Ká jẹ́ kí ẹni yíyẹ

    Mọ̀ pé Ìjọba Jèhófà

    Nìkan ló ṣeé gbọ́kàn lé.

    (ÈGBÈ)

    Ẹ kọ́kọ́ wá Ìjọba náà

    Àtòdodo Jèhófà.

    Ká pòkìkí rẹ̀ fáráyé,

    Ká sì máa fòtítọ́ sìn ín.