ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN | LÉFÍTÍKÙ 16-17

Bí Ọjọ́ Ètùtù Ṣe Kàn Ẹ́

Bí Ọjọ́ Ètùtù Ṣe Kàn Ẹ́

16:12-15

Kí la rí kọ́ látinú bí wọ́n ṣe ń sun tùràrí ní Ọjọ́ Ètùtù?

  • Jèhófà máa ń gbọ́ àdúrà àwọn olóòótọ́, torí ó dà bíi tùràrí lójú ẹ̀. (Sm 141:2) Bí àlùfáà àgbà ṣe máa ń sun tùràrí níwájú Jèhófà pẹ̀lú ọ̀wọ̀ jíjinlẹ̀, bẹ́ẹ̀ náà ló ṣe yẹ ká máa gbàdúrà sí Jèhófà tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀

  • Àlùfáà àgbà gbọ́dọ̀ sun tùràrí kó tó lè rúbọ. Bákan náà, kí Jésù tó fi ara rẹ̀ rúbọ, ó ṣe ohun tó mú kí Jèhófà tẹ́wọ́ gba ẹbọ rẹ̀ torí pé ó pa ìwà títọ́ mọ́, ó sì jẹ́ olóòótọ́

Kí ni màá ṣe tí mo bá fẹ́ kí Jèhófà tẹ́wọ́ gba ohun tí mò ń ṣe nínú ìjọsìn rẹ̀?