ORIN 80

‘Tọ́ Ọ Wò, Kó O sì Rí I Pé Ẹni Rere Ni Jèhófà’

‘Tọ́ Ọ Wò, Kó O sì Rí I Pé Ẹni Rere Ni Jèhófà’

(Sáàmù 34:8)

  1. 1. Ayọ̀ tá a ní kò láfiwé;

    A láǹfààní láti wàásù.

    Tọkàntọkàn ni ká fi ṣiṣẹ́ náà

    Ká lè ráwọn ẹni yíyẹ.

    (ÈGBÈ)

    Tọ́ ọ wò, kó o sì rí adùn rẹ̀ pé

    Jèhófà jẹ́ni rere.

    Bá a ṣe ń fọkàn sin Ọlọ́run wa,

    Ó ń bù kún ìsapá wa.

  2. 2. A mọyì àwọn ará wa

    Tó jẹ́ alákòókò kíkún.

    Ọ̀pọ̀ ìbùkún ń dúró de àwọn

    Tó fara síṣẹ́ Jèhófà.

    (ÈGBÈ)

    Tọ́ ọ wò, kó o sì rí adùn rẹ̀ pé

    Jèhófà jẹ́ni rere.

    Bá a ṣe ń fọkàn sin Ọlọ́run wa,

    Ó ń bù kún ìsapá wa.