December 8-14
ÀÌSÁYÀ 6-8
Orin 75 àti Àdúrà | Ọ̀rọ̀ Ìbẹ̀rẹ̀ (1 min.)
1. “Èmi Nìyí! Rán Mi!”
(10 min.)
Àìsáyà ò rò ó lẹ́ẹ̀mejì kó tó gbà láti ṣiṣẹ́ wòlíì fún Jèhófà (Ais 6:8; ip-1 93-94 ¶13-14)
Iṣẹ́ tí Jèhófà gbé fún Àìsáyà ò rọrùn (Ais 6:9, 10; ip-1 95 ¶15-16)
Bí ọ̀pọ̀ èèyàn ò ṣe fetí sí ọ̀rọ̀ Àìsáyà, bẹ́ẹ̀ náà ni wọn ò fetí sọ́rọ̀ Jésù (Mt 13:13-15; ip-1 99 ¶23)
RONÚ LÓRÍ ÌBÉÈRÈ YÌÍ: Báwo ni mo ṣe lè ṣe púpọ̀ sí i lẹ́nu iṣẹ́ Jèhófà bí Àìsáyà?
2. Àwọn Ẹ̀kọ́ Iyebíye Míì
(10 min.)
-
Ais 7:3, 4—Kí nìdí tí Jèhófà fi dáàbò bo Ọba Áhásì tó jẹ́ ẹni burúkú? (w06 12/1 9 ¶4)
-
Àwọn ẹ̀kọ́ iyebíye wo lo rí nínú Bíbélì kíkà ọ̀sẹ̀ yìí tí wàá fẹ́ sọ?
3. Bíbélì Kíkà
(4 min.) Ais 8:1-13 (th ẹ̀kọ́ 5)
4. Bá A Ṣe Lè Bẹ̀rẹ̀ Ọ̀rọ̀ Wa
(3 min.) ÌWÀÁSÙ ILÉ-DÉ-ILÉ. Lo ọ̀kan nínú àwọn àkòrí tó wà ní àfikún A nínú ìwé Nífẹ̀ẹ́ Àwọn Èèyàn láti bá ẹnì kan sọ̀rọ̀. (lmd ẹ̀kọ́ 4 kókó 5)
5. Pa Dà Lọ
(4 min.) ÌWÀÁSÙ ILÉ-DÉ-ILÉ. Fi ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì lọ ẹni náà. (lmd ẹ̀kọ́ 9 kókó 3)
6. Pa Dà Lọ
(5 min.) ÌWÀÁSÙ ILÉ-DÉ-ILÉ. Fi bá a ṣe ń ṣe ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì han ẹni náà. (lmd ẹ̀kọ́ 9 kókó 5)
Orin 83
7. Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà Máa Ń Wàásù Láti Ilé Dé Ilé
(15 min.) Ìjíròrò.
Àwọn èèyàn mọ àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà dáadáa pé a máa ń wàásù láti ilé dé ilé, ohun tí Jésù àtàwọn Kristẹni àkọ́bẹ̀rẹ̀ náà sì ṣe nìyẹn.—Lk 10:5; Iṣe 5:42.
Àmọ́, a ní láti dá iṣẹ́ ìwàásù ilé-dé-ilé dúró nígbà àjàkálẹ̀ àrùn Kòrónà. A bẹ̀rẹ̀ sí í wàásù láwọn ọ̀nà míì, irú bíi ká fi tẹlifóònù wàásù tàbí ká kọ lẹ́tà. A tún máa ń wàásù fáwọn èèyàn tá a bá pàdé lọ́jà, nínú mọ́tò tàbí láwọn ibòmíì. Inú wa sì dùn torí ó ti wá mọ́ wa lára láti máa wàásù láwọn ọ̀nà míì. Síbẹ̀, ìwàásù ilé-dé-ilé ni ọ̀nà tó ṣe pàtàkì jù tá à ń gbà wàásù ìhìn rere. Torí náà tó bá ṣeé ṣe fún ẹ, rí i pé ò ń lọ́wọ́ sí ìwàásù ilé-dé-ilé déédéé.
Tá a bá ń wàásù láti ilé de ilé, báwo ló ṣe máa ràn wá lọ́wọ́ láti ṣe àwọn nǹkan yìí?
-
Ká wàásù fún gbogbo àwọn tó wà ní ìpínlẹ̀ ìwàásù wa
-
Kí ọ̀nà tá à ń gbà kọ́ àwọn èèyàn dáa sí, ká túbọ̀ ní ìgboyà, ká má ṣojúsàájú, ká sì ṣe tán láti yááfì àwọn nǹkan fún iṣẹ́ Ọlọ́run
-
Ká bẹ̀rẹ̀ ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì
Jẹ́ kí àwọn ará wo FÍDÍÒ À Ń Wàásù Láìka Bójú Ọjọ́ Ṣe Rí. Lẹ́yìn náà, béèrè pé:
-
Kí la kọ́ lára àwọn ará tó wà ní erékùṣù Faroe?
8. Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Ìjọ
(30 min.) lfb ẹ̀kọ́ 42-43

