Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

Mú Kí Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Rẹ Sunwọ̀n Sí I​—Máa Wàásù fún Àwọn Afọ́jú

Mú Kí Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Rẹ Sunwọ̀n Sí I​—Máa Wàásù fún Àwọn Afọ́jú

ÌDÍ TÓ FI ṢE PÀTÀKÌ: Ọ̀pọ̀ àwọn afọ́jú ni kì í fẹ́ bá àwọn tí wọn ò mọ̀ rí sọ̀rọ̀. Torí náà, ó máa ń gba ọgbọ́n ká tó lè wàásù fún wọn. Jèhófà ò fọ̀rọ̀ àwọn afọ́jú ṣeré rárá. (Le 19:14) Àwa náà lè tẹ̀ lé àpẹẹrẹ rẹ̀ tá a bá ń wá bá a ṣe máa ràn wọ́n lọ́wọ́ kí wọ́n lè mọ Ọlọ́run.

BÓ O ṢE LÈ ṢE É:

  • “Wá” àwọn afọ́jú lọ. (Mt 10:11) Ṣé o mọ ẹnì kan tí afọ́jú wà nínú ìdílé rẹ̀? Ṣé ilé ìwé àwọn afọ́jú wà ní ìpínlẹ̀ ìwàásù yín tàbí àwọn àjọ tó ń pèsè ìrànwọ́ fún àwọn afọ́jú tàbí ibi tí wọ́n ti ń tọ́jú àwọn afọ́jú? Ṣé ó ṣeé ṣe kí wọ́n nífẹ̀ẹ́ sí àwọn ìwé wa tó wà lédè àwọn afọ́jú?

  • Fi hàn pé o nífẹ̀ẹ́ wọn. Tó o bá ṣe ohun tó fi hàn pé ọ̀rọ̀ wọn jẹ ẹ́ lọ́kàn, tó o sì fi tẹ̀rín tọ̀yàyà bá wọn sọ̀rọ̀, ìyẹn á jẹ́ kára tù wọ́n. O lè fi ohun tí wọ́n máa nífẹ̀ẹ́ sí bẹ̀rẹ̀ ìjíròrò rẹ

  • Ràn wọ́n lọ́wọ́ kí wọ́n lè sún mọ́ Jèhófà. Ètò Ọlọ́run ti pèsè onírúurú ìtẹ̀jáde ká lè ṣèrànwọ́ fáwọn afọ́jú àtàwọn tí kò fi bẹ́ẹ̀ ríran dáadáa. O lè bi í pé èwo ló nífẹ̀ẹ́. Kí alábòójútó iṣẹ́ ìsìn rí i pé ìránṣẹ́ ìwé ìkẹ́kọ̀ọ́ béèrè fún irú èyí tí afọ́jú tó wà ládùúgbò yín bá nífẹ̀ẹ́ sí