January 5-11
ÀÌSÁYÀ 17-20
Orin 153 àti Àdúrà | Ọ̀rọ̀ Ìbẹ̀rẹ̀ (1 min.)
1. “Ìpín Àwọn Tó Ń Kó Wa Lẹ́rù”
(10 min.)
Bíbélì fi aráyé wé omi òkun tó ń ru gùdù, tí kò ní àlàáfíà (Ais 17:12; w18.06 7 ¶16)
A mọ̀ pé àwọn èèyàn máa hùwà àìdáa sí wa torí pé a kì í dá sí ọ̀rọ̀ òṣèlú (Jo 15:18, 19; w16.04 22 ¶4)
Láìpẹ́, Jèhófà máa gbà wá lọ́wọ́ “àwọn tó ń kó wa lẹ́rù” (Ais 17:13, 14; ip-1 198 ¶20)
2. Àwọn Ẹ̀kọ́ Iyebíye Míì
(10 min.)
-
Ais 20:2—Ṣé òótọ́ ni pé Àìsáyà rìn kiri níhòòhò fún ọdún mẹ́ta? (w06 12/1 11 ¶2)
-
Àwọn ẹ̀kọ́ iyebíye wo lo rí nínú Bíbélì kíkà ọ̀sẹ̀ yìí tí wàá fẹ́ sọ?
3. Bíbélì Kíkà
(4 min.) Ais 19:1-12 (th ẹ̀kọ́ 11)
4. Bá A Ṣe Lè Bẹ̀rẹ̀ Ọ̀rọ̀ Wa
(3 min.) ÌWÀÁSÙ ILÉ-DÉ-ILÉ. Lo ọ̀kan nínú àwọn àkòrí tó wà ní àfikún A nínú ìwé Nífẹ̀ẹ́ Àwọn Èèyàn láti bá ọkọ tàbí ìyàwó kan sọ̀rọ̀. (lmd ẹ̀kọ́ 2 kókó 3)
5. Pa Dà Lọ
(4 min.) ÌWÀÁSÙ ILÉ-DÉ-ILÉ. Fi ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì lọ ẹni náà. (lmd ẹ̀kọ́ 8 kókó 4)
6. Àsọyé
(5 min.) lmd àfikún A kókó 14—Àkòrí: Ọlọ́run Fẹ́ Ká Máa Gbàdúrà sí Òun. (th ẹ̀kọ́ 8)
Orin 148
7. “Rántí Àpáta Ààbò Rẹ”
(10 min.) Ìjíròrò.
Jèhófà ni àpáta ààbò wa. (Ais 17:10) Ó máa dáàbò bo àwọn tó bá sá lọ sọ́dọ̀ ẹ̀. (Sm 144:1, 2) Òótọ́ ni pé Jèhófà kì í yọ wá kúrò nínú gbogbo àdánwò, àmọ́ gbogbo ìgbà ló máa ń ràn wá lọ́wọ́ ká lè fara dà á.—1Kọ 10:13.
Ohun kan tá a lè ṣe táá fi hàn pé a rántí Jèhófà ni pé ká máa ṣègbọràn sí i. Jẹ́ kí àwọn ará wo FÍDÍÒ Kẹ́kọ̀ọ́ Lára Àwọn Ọ̀rẹ́ Jèhófà—Hananáyà, Míṣáẹ́lì àti Asaráyà. O lè pe àwọn ọmọdé mélòó kan wá sórí pèpéle tàbí kó o bi àwọn ará pé:
-
Báwo ni Jèhófà ṣe gba àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ sílẹ̀?—Da 3:24-28
-
Báwo ni Hananáyà, Míṣáẹ́lì àti Asaráyà ṣe fi hàn pé ọ̀rẹ́ Jèhófà làwọn?
-
Ìgbà wo ló máa ń ṣòro fún ẹ láti ṣègbọràn sí Jèhófà?
-
Àwọn nǹkan wo ló máa jẹ́ kó o lè máa ṣègbọràn sí Jèhófà?
8. Máa Wáyè Kẹ́kọ̀ọ́ Lára Àwọn Ọ̀rẹ́ Jèhófà Lójoojúmọ́
(5 min.) Ìjíròrò.
Àwọn ọmọ tó ṣẹ̀ṣẹ̀ ń kọ́ bí wọ́n ṣe ń kàwé la ṣe àwọn fídíò Kẹ́kọ̀ọ́ Lára Àwọn Ọ̀rẹ́ Jèhófà fún. Ó máa jẹ́ kí wọ́n mọ̀ nípa àwọn tó nífẹ̀ẹ́ Jèhófà, kí wọ́n sì kẹ́kọ̀ọ́ lára wọn. Ọ̀kọ̀ọ̀kan àwọn fídíò yẹn máa ń rọ àwọn ọmọdé pé kí wọ́n “máa wáyè kẹ́kọ̀ọ́ lára àwọn ọ̀rẹ́ Jèhófà lójoojúmọ́.”
-
Kí lo lè ṣe kó o lè máa ráyè kẹ́kọ̀ọ́ lára àwọn ọ̀rẹ́ Jèhófà lójoojúmọ́?
-
Èwo nínú àwọn tí Bíbélì sọ̀rọ̀ wọn ni wàá fẹ́ mọ̀ sí i nípa ẹ̀, kí sì nìdí?
9. Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Ìjọ
(30 min.) lfb ẹ̀kọ́ 50, ọ̀rọ̀ ìbẹ̀rẹ̀ apá 9 àti ẹ̀kọ́ 51

