ÌWÉ ÌPÀDÉ ÌGBÉSÍ AYÉ ÀTI IṢẸ́ ÒJÍṢẸ́ ÀWA KRISTẸNI

Ìtòlẹ́sẹẹsẹ Ìpàdé Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ ti January 19-25, 2026

Yorùbá
Ìtòlẹ́sẹẹsẹ Ìpàdé Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ ti January 19-25, 2026
https://cms-imgp.jw-cdn.org/img/p/202026003/univ/art/202026003_univ_sqr_xl.jpg
mwb26 January ojú ìwé 6-7

January 19-25

ÀÌSÁYÀ 24-27

January 19-25

Orin 159 àti Àdúrà | Ọ̀rọ̀ Ìbẹ̀rẹ̀ (1 min.)

ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN

1. “Ọlọ́run Wa Nìyí!”

(10 min.)

Inú wa dùn pé Jèhófà ni Ọlọ́run wa (Ais 25:9; cl 15 ¶21)

Ọ̀pọ̀ nǹkan rere la máa gbádùn nínú ayé tuntun, títí kan ọ̀pọ̀ yanturu oúnjẹ aládùn (Ais 25:6; w24.12 6 ¶14)

Ó máa fún wa ní ìyè àìnípẹ̀kun (Ais 25:7, 8; w25.01 28-29 ¶11-12)

RONÚ LÓRÍ ÌBÉÈRÈ YÌÍ, ‘Ta ni mo lè sọ àwọn ìlérí Jèhófà fún lọ́sẹ̀ yìí?’

2. Àwọn Ẹ̀kọ́ Iyebíye Míì

(10 min.)

  • Ais 24:2—Kí nìdí tí ọ̀nà tí wọ́n gbà kọ ẹsẹ yìí nínú Bíbélì tá a tún ṣe fi yàtọ̀ sí ti Bíbélì tá à ń lò tẹ́lẹ̀? (w15 12/15 17 ¶2-4)

  • Àwọn ẹ̀kọ́ iyebíye wo lo rí nínú Bíbélì kíkà ọ̀sẹ̀ yìí tí wàá fẹ́ sọ?

3. Bíbélì Kíkà

TẸRA MỌ́ IṢẸ́ ÌWÀÁSÙ

4. Bá A Ṣe Lè Bẹ̀rẹ̀ Ọ̀rọ̀ Wa

(3 min.) ÌWÀÁSÙ NÍBI TÍ ÈRÒ PỌ̀ SÍ. Fọgbọ́n wádìí ohun tó ń jẹ ẹni náà lọ́kàn, kó o sì fi bó ṣe lè rí ohun tó máa ràn án lọ́wọ́ hàn án lórí ìkànnì jw.org. (lmd ẹ̀kọ́ 1 kókó 3)

5. Pa Dà Lọ

(4 min.) ÌWÀÁSÙ ILÉ-DÉ-ILÉ. Lo ọ̀kan nínú àwọn àkòrí tó wà ní àfikún A nínú ìwé Nífẹ̀ẹ́ Àwọn Èèyàn láti bá ẹni náà sọ̀rọ̀. (lmd ẹ̀kọ́ 9 kóko 4)

6. Ṣàlàyé Ohun Tó O Gbà Gbọ́

(5 min.) Àṣefihàn. ijwbq àpilẹ̀kọ 160—Àkòrí: Kí Nìdí Tí A Fi Pe Jésù Ní Ọmọ Ọlọ́run? (th ẹ̀kọ́ 3)

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

Orin 144

7. Gbára Lé Jèhófà Pátápátá Tó O Bá Fẹ́ Gba Ìtọ́jú Nílé Ìwòsàn Tàbí Tó O Fẹ́ Ṣiṣẹ́ Abẹ

(15 min.) Ìjíròrò.

Jèhófà máa ń dáàbò bo ‘àwọn tó gbára lé e pátápátá.’ (Ka Àìsáyà 26:3.) Tá a bá fẹ́ gba ìtọ́jú nílé ìwòsàn, a lè fi hàn pé a gbára lé Jèhófà pátápátá tá a bá ń lo àwọn nǹkan tí ètò ẹ̀ ti pèsè fún wa.

Jẹ́ kí àwọn ará wo FÍDÍÒ Ṣé O Ti Múra Sílẹ̀ De Ìtọ́jú Pàjáwìrì? Lẹ́yìn náà, béèrè pé:

  • Àwọn nǹkan mẹ́ta wo ni ètò Ọlọ́run ní ká ṣe ká tó lọ gba ìtọ́jú nílé ìwòsàn?

  • Báwo ni onírúurú ìsọfúnni tí ètò Ọlọ́run ti fún wa a nípa ọ̀rọ̀ ìtọ́jú ṣe lè ràn wá lọ́wọ́?

  • Ìgbà wo ló yẹ ká kàn sí Ìgbìmọ̀ Alárinà Ilé Ìwòsàn?

  • Báwo ni ètò onífẹ̀ẹ́ tí Jèhófà pèsè yìí ṣe rí lára ẹ?

“Àlàáfíà tí kò lópin” tí Jèhófà ṣèlérí ní Àìsáyà 26:3 ò túmọ̀ sí pé a ò ní ṣàìsàn rárá. Kàkà bẹ́ẹ̀, àwọn ètò ìrànwọ́ tí Jèhófà ti pèsè yìí máa ń jẹ́ kí ọkàn wa balẹ̀, kí ara sì tù wá lásìkò tá a bá ń gba ìtọ́jú nílé ìwòsàn.

8. Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Ìjọ

Ọ̀rọ̀ Ìparí (3 min.) | Orin 53 àti Àdúrà

a O lè gba àwọn ìsọfúnni yìí lọ́wọ́ àwọn alàgbà nígbà tó o bá nílò ẹ̀. Ìsọfúnni fún Àwọn Aláboyún (S-401), Ìsọfúnni fún Àwọn tó Nílò Iṣẹ́ Abẹ Tàbí Ìtọ́jú Chemotherapy (S-407) àti Báwọn Òbí Ṣe Lè Dáàbò Bo Àwọn Ọmọ Wọn Kí Wọ́n Má Bàá Fa Ẹ̀jẹ̀ sí Wọn Lára (S-55).