ÌWÉ ÌPÀDÉ ÌGBÉSÍ AYÉ ÀTI IṢẸ́ ÒJÍṢẸ́ ÀWA KRISTẸNI

Ìtòlẹ́sẹẹsẹ Ìpàdé Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ ti February 2-8, 2026

Yorùbá
Ìtòlẹ́sẹẹsẹ Ìpàdé Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ ti February 2-8, 2026
https://cms-imgp.jw-cdn.org/img/p/202026005/univ/art/202026005_univ_sqr_xl.jpg
mwb26 January ojú ìwé 10

February 2-8

ÀÌSÁYÀ 30-32

February 2-8

Orin 8 àti Àdúrà | Ọ̀rọ̀ Ìbẹ̀rẹ̀ (1 min.)

ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN

1. Gbà Pé Jèhófà Máa Dáàbò Bò Ẹ́

(10 min.)

Bí ẹyẹ ṣe ń dáàbò bo àwọn ọmọ ẹ̀ lọ́wọ́ àwọn tó fẹ́ pa wọ́n jẹ, bẹ́ẹ̀ náà ni Jèhófà máa ń dáàbò bo àwa èèyàn rẹ̀ (Ais 31:5; w01 11/15 17 ¶7)

Má ṣe yẹra fáwọn tí Jèhófà ń lò láti ràn ẹ́ lọ́wọ́ (Ais 32:1, 2; w24.01 24 ¶13)

Máa ronú nípa ìlérí tí Jèhófà ti ṣe fún ẹ, ìyẹn á jẹ́ kó o túbọ̀ lókun (Ais 32:16-18; w23.10 17 ¶19)

2. Àwọn Ẹ̀kọ́ Iyebíye Míì

(10 min.)

  • Ais 30:20—Kí ló túmọ̀ sí nígbà tí Àìsáyà sọ pé Jèhófà máa fi “wàhálà ṣe oúnjẹ fún yín, tó sì máa fi ìyà ṣe omi fún yín”? (ip-1 310 ¶17)

  • Àwọn ẹ̀kọ́ iyebíye wo lo rí nínú Bíbélì kíkà ọ̀sẹ̀ yìí tí wàá fẹ́ sọ?

3. Bíbélì Kíkà

TẸRA MỌ́ IṢẸ́ ÌWÀÁSÙ

4. Bá A Ṣe Lè Bẹ̀rẹ̀ Ọ̀rọ̀ Wa

(4 min.) ÌWÀÁSÙ ÀÌJẸ́-BÍ-ÀṢÀ. Ẹni náà sọ bí ohun kan tó ṣẹlẹ̀ lẹ́nu àìpẹ́ yìí ṣe ń kó o lọ́kàn sókè. (lmd ẹ̀kọ́ 2 kókó 5)

5. Bá A Ṣe Lè Bẹ̀rẹ̀ Ọ̀rọ̀ Wa

(4 min.) ÌWÀÁSÙ ILÉ-DÉ-ILÉ. (lmd ẹ̀kọ́ 5 kókó 5)

6. Pa Dà Lọ

(4 min.) ÌWÀÁSÙ ILÉ-DÉ-ILÉ. Fi ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì lọ ẹni náà. (lmd ẹ̀kọ́ 7 kókó 3)

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

Orin 157

7. “Àlàáfíà Ni Òdodo Tòótọ́ Máa Mú Wá”—Àyọlò

(15 min.) Ìjíròrò.

Jẹ́ kí àwọn ará wo FÍDÍÒ náà. Lẹ́yìn náà, béèrè pé:

  • Kí lo rí kọ́ nínú fídíò yìí tó bá di pé ká fara mọ́ ìlànà òdodo Jèhófà?—Ais 32:17.

8. Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Ìjọ

Ọ̀rọ̀ Ìparí (3 min.) | Orin 133 àti Àdúrà