February 16-22
ÀÌSÁYÀ 36-37
Orin 150 àti Àdúrà | Ọ̀rọ̀ Ìbẹ̀rẹ̀ (1 min.)
1. “Má Bẹ̀rù Nítorí Àwọn Ọ̀rọ̀ Tí O Gbọ́”
(10 min.)
Rábúṣákè lọ sí Jerúsálẹ́mù kó lè dẹ́rù ba àwọn èèyàn Jèhófà (Ais 36:1, 2; it “Hẹsikáyà” No. 1 ¶14)
Ó fẹ́ kó jìnnìjìnnì bá wọn, kí wọ́n sì rò pé kò sẹ́ni tó lè gbà wọ́n (Ais 36:8; ip-1 387 ¶10)
Ó ń fi wọ́n ṣe yẹ̀yẹ́ torí wọ́n gbẹ́kẹ̀ lé Jèhófà àti Hẹsikáyà ọba wọn (Ais 36:7, 18-20; ip-1 388 ¶13-14)
Kò sídìí tó fi yẹ káwa èèyàn Jèhófà máa bẹ̀rù àwọn tó ń halẹ̀ mọ́ wa.—Ais 37:6, 7
OHUN TẸ́ Ẹ LÈ ṢE NÍGBÀ ÌJỌSÌN ÌDÍLÉ: Ẹ wo FÍDÍÒ náà “Jèhófà . . . Ìwọ Ni Mo Gbẹ́kẹ̀ Lé,” kẹ́ ẹ sì jíròrò ohun tẹ́ ẹ kọ́ níbẹ̀.
2. Àwọn Ẹ̀kọ́ Iyebíye Míì
(10 min.)
-
Ais 37:29—Kí ló túmọ̀ sí nígbà tí Jèhófà sọ pé òun máa fi ìjánu sáàárín ètè Ọba Senakérúbù? (it “Ìjánu” ¶4)
-
Àwọn ẹ̀kọ́ iyebíye wo lo rí nínú Bíbélì kíkà ọ̀sẹ̀ yìí tí wàá fẹ́ sọ?
3. Bíbélì Kíkà
(4 min.) Ais 37:14-23 (th ẹ̀kọ́ 2)
4. Bá A Ṣe Lè Bẹ̀rẹ̀ Ọ̀rọ̀ Wa
(3 min.) ÌWÀÁSÙ ILÉ-DÉ-ILÉ. Lo ọ̀kan nínú àwọn àkòrí tó wà ní àfikún A nínú ìwé Nífẹ̀ẹ́ Àwọn Èèyàn láti bá ẹni náà sọ̀rọ̀. (lmd ẹ̀kọ́ 1 kókó 4)
5. Bá A Ṣe Lè Bẹ̀rẹ̀ Ọ̀rọ̀ Wa
(4 min.) ÌWÀÁSÙ ÀÌJẸ́-BÍ-ÀṢÀ. (lmd ẹ̀kọ́ 3 kókó 5)
6. Ṣàlàyé Ohun Tó O Gbà Gbọ́
(5 min.) Àṣefihàn. ijwbq àpilẹ̀kọ 110 ¶1-4—Àkòrí: Kí Ni Ìrìbọmi Túmọ̀ Sí? (th ẹ̀kọ́ 17)
Orin 118
7. “Kí Lo Gbọ́kàn Lé?”
(15 min.) Ìjíròrò.
Ṣé ẹnì kan ti fi ẹ́ ṣe yẹ̀yẹ́ rí torí pé o gba Ọlọ́run gbọ́ tàbí torí pé o gba ohun tí Bíbélì sọ gbọ́? Ṣé wọ́n ti bú ẹ rí torí pé o jẹ́ Ẹlẹ́rìí Jèhófà? Tó bá jẹ́ bẹ́ẹ̀, ẹ̀rù lè bẹ̀rẹ̀ sí í bà ẹ́, kó o má sì mọ ohun tó o máa sọ. Kódà irú nǹkan bẹ́ẹ̀ lè mú kó o máa ṣiyèméjì. Kí lo lè ṣe tó ò fi ní máa bẹ̀rù tàbí ṣiyèméjì?
Ka Àìsáyà 36:4. Lẹ́yìn náà, béèrè pé:
-
Kí nìdí tó fi ṣe pàtàkì kí ohun tá a gbà gbọ́ dá wa lójú?
Jẹ́ kí àwọn ará wo FÍDÍÒ Ìgbà Ọ̀dọ́ Mi—Ṣé Ó Bọ́gbọ́n Mu Ká Gbà Pé Ọlọ́run Wà? Lẹ́yìn náà, béèrè pé:
-
Kí ni Elibaldo àti Crystal ṣe kí ohun tí Bíbélì sọ lè túbọ̀ dá wọn lójú?
-
Kí ló jẹ́ kó dá ẹ lójú pé Ọlọ́run wà?
-
Àwọn ẹsẹ Bíbélì wo ló jẹ́ kó dá ẹ lójú pé . . .
Jèhófà nífẹ̀ẹ́ ẹ?
gbogbo ìgbà ni Jèhófà máa ràn ẹ́ lọ́wọ́?
o ti rí ìsìn tòótọ́?
8. Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Ìjọ
(30 min.) lfb ẹ̀kọ́ 62-63

