Sáàmù 95:1-11
95 Ẹ wá, ẹ jẹ́ ká kígbe ayọ̀ sí Jèhófà!
Ẹ jẹ́ ká kígbe ìṣẹ́gun sí Àpáta ìgbàlà wa.+
2 Ẹ jẹ́ ká wá sí iwájú* rẹ̀ pẹ̀lú ọpẹ́;+Ẹ jẹ́ ká kọrin, ká sì kígbe ìṣẹ́gun sí i.
3 Nítorí pé Ọlọ́run ńlá ni Jèhófà,Ọba ńlá lórí gbogbo àwọn ọlọ́run yòókù.+
4 Ọwọ́ rẹ̀ ni ọ̀gbun ayé wà;Àwọn téńté orí òkè jẹ́ tirẹ̀.+
5 Òkun jẹ́ tirẹ̀, òun ló dá a,+Ọwọ́ rẹ̀ ló sì dá ilẹ̀ gbígbẹ.+
6 Ẹ wá, ẹ jẹ́ ká jọ́sìn, ká sì forí balẹ̀;Ẹ jẹ́ ká kúnlẹ̀ níwájú Jèhófà Ẹni tó dá wa.+
7 Nítorí òun ni Ọlọ́run wa,Àwa sì ni èèyàn ibi ìjẹko rẹ̀,Àgùntàn tó wà lábẹ́ àbójútó rẹ̀.*+
Lónìí, tí ẹ bá fetí sí ohùn rẹ̀,+
8 Ẹ má ṣe mú kí ọkàn yín le bí ẹ ṣe ṣe ní Mẹ́ríbà,*+Bíi ti ọjọ́ Másà* ní aginjù,+
9 Nígbà tí àwọn baba ńlá yín dán mi wò;+Wọ́n pè mí níjà, bó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n ti rí àwọn iṣẹ́ mi.+
10 Ogójì (40) ọdún ni mo fi kórìíra ìran yẹn, mo sì sọ pé:
“Àwọn èèyàn tó máa ń ṣìnà nínú ọkàn wọn ni wọ́n;Wọn ò tíì mọ àwọn ọ̀nà mi.”
11 Torí náà, mo búra nínú ìbínú mi pé:
“Wọn ò ní wọnú ìsinmi mi.”+

