Sáàmù 92:1-15

  • Jèhófà, ẹni gíga ni ọ́ títí láé

    • Àwọn iṣẹ́ rẹ̀ tóbi, èrò rẹ̀ sì jinlẹ̀ (5)

    • “Olódodo máa gbilẹ̀ bí igi” (12)

    • Àwọn arúgbó á máa lókun (14)

Orin atunilára. Orin ọjọ́ Sábáàtì. 92  Ó dára láti máa fi ọpẹ́ fún Jèhófà+Àti láti máa fi orin yin* orúkọ rẹ, ìwọ Ẹni Gíga Jù Lọ,   Láti máa kéde ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀+ ní àárọ̀Àti òtítọ́ rẹ ní òru,   Pẹ̀lú ohun ìkọrin olókùn tín-ín-rín mẹ́wàá àti gòjé,Nípasẹ̀ háàpù tó ń dún dáadáa.+   Jèhófà, ò ń mú inú mi dùn, nítorí àwọn ohun tí ò ń ṣe;Mò ń kígbe ayọ̀ nítorí àwọn iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.   Àwọn iṣẹ́ rẹ mà tóbi o, Jèhófà!+ Èrò rẹ jinlẹ̀ gidigidi!+   Kò sí aláìnírònú tó lè mọ̀ wọ́n;Kò sì sí òmùgọ̀ tó lè lóye èyí:+   Nígbà tí àwọn ẹni burúkú bá rú jáde bíi koríko*Tí gbogbo àwọn aṣebi sì gbilẹ̀,Kí wọ́n lè pa run títí láé ni.+   Àmọ́, ẹni gíga ni ọ́ títí láé, Jèhófà.   Wo ìṣubú àwọn ọ̀tá rẹ, Jèhófà,Wo bí àwọn ọ̀tá rẹ ṣe máa ṣègbé;Gbogbo àwọn aṣebi yóò tú ká.+ 10  Àmọ́ wàá mú kí agbára mi pọ̀ sí i* bíi ti akọ màlúù igbó;Màá fi òróró dáradára para.+ 11  Ojú mi á rí ìṣubú àwọn ọ̀tá mi;+Etí mi á gbọ́ nípa ìṣubú àwọn aṣebi tó ń bá mi jà. 12  Àmọ́ olódodo máa gbilẹ̀ bí igi ọ̀pẹWọ́n á sì tóbi bí igi kédárì ní Lẹ́bánónì.+ 13  Ilé Jèhófà ni a gbìn wọ́n sí;Wọ́n ń gbilẹ̀ ní àwọn àgbàlá Ọlọ́run wa.+ 14  Kódà nígbà arúgbó* wọn, wọ́n á máa lókun;+Wọ́n á ṣì máa ta kébé,* ara wọn á sì máa dán,+ 15  Láti máa kéde pé adúróṣinṣin ni Jèhófà. Òun ni Àpáta+ mi, ẹni tí kò sí àìṣòdodo nínú rẹ̀.

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “kọrin sí.”
Tàbí “èpò.”
Ní Héb., “wàá gbé ìwo mi ga.”
Tàbí “nígbà orí ewú.”
Ní Héb., “Wọ́n á sanra.”