Sáàmù 9:1-20

  • Ìkéde àwọn iṣẹ́ àgbàyanu Ọlọ́run

    • Jèhófà jẹ́ ibi ààbò tó dájú (9)

    • Mímọ orúkọ Ọlọ́run ń mú ká gbẹ́kẹ̀ lé e (10)

Sí olùdarí; lórí Muti-lábénì.* Orin Dáfídì. א [Áléfì] 9  Jèhófà, màá fi gbogbo ọkàn mi yìn ọ́;Màá sọ nípa gbogbo iṣẹ́ àgbàyanu rẹ.+   Ṣe ni inú mi á máa dùn, tí màá sì máa yọ̀ nínú rẹ;Màá fi orin yin* orúkọ rẹ, ìwọ Ẹni Gíga Jù Lọ.+ ב [Bétì]   Nígbà tí àwọn ọ̀tá mi bá sá pa dà,+Wọ́n á ṣubú, wọ́n á sì ṣègbé kúrò níwájú rẹ.   Nítorí pé o gbèjà mi lórí ẹ̀tọ́ mi;O jókòó sórí ìtẹ́ rẹ, o sì ń fi òdodo ṣe ìdájọ́.+ ג [Gímélì]  O ti bá àwọn orílẹ̀-èdè wí,+ o sì ti pa àwọn ẹni burúkú run,O ti nu orúkọ wọn kúrò títí láé àti láéláé.  Ọ̀tá ti pa run títí láé;O ti fa àwọn ìlú wọn tu,Wọn yóò sì di ẹni ìgbàgbé.+ ה [Híì]  Àmọ́ Jèhófà wà lórí ìtẹ́ títí láé;+Ó ti fìdí ìtẹ́ rẹ̀ múlẹ̀ gbọn-in láti máa ṣe ìdájọ́ òdodo.+  Yóò fi òdodo ṣe ìdájọ́ ilẹ̀ ayé tí à ń gbé;*+Yóò dá ẹjọ́ òdodo fún àwọn orílẹ̀-èdè.+ ו [Wọ́ọ̀]   Jèhófà yóò di ibi ààbò* fún àwọn tí à ń ni lára,+Ibi ààbò ní àkókò wàhálà.+ 10  Àwọn tó mọ orúkọ rẹ yóò gbẹ́kẹ̀ lé ọ;+Jèhófà, ìwọ kì yóò pa àwọn tó ń wá ọ tì láé.+ ז [Sáyìn] 11  Ẹ kọ orin ìyìn sí Jèhófà, ẹni tó ń gbé ní Síónì;Ẹ jẹ́ kí àwọn èèyàn mọ àwọn ohun tí ó ṣe.+ 12  Nítorí Ẹni tó ń gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ wọn ń rántí wọn;+Kò ní gbàgbé igbe àwọn tí ìyà ń jẹ.+ ח [Hétì] 13  Ṣojú rere sí mi, Jèhófà; wo ìyà tí àwọn tó kórìíra mi fi ń jẹ mí,Ìwọ tó gbé mi dìde láti àwọn ẹnubodè ikú,+ 14  Kí n lè máa kéde àwọn iṣẹ́ rẹ tí ó yẹ fún ìyìn ní àwọn ẹnubodè ọmọbìnrin Síónì,+Kí àwọn iṣẹ́ ìgbàlà rẹ sì lè máa mú inú mi dùn.+ ט [Tétì] 15  Àwọn orílẹ̀-èdè ti rì sínú kòtò tí wọ́n gbẹ́;Ẹsẹ̀ wọn ti kó sínú àwọ̀n tí àwọn fúnra wọn dẹ pa mọ́.+ 16  Àwọn ìdájọ́ tí Jèhófà ń mú ṣẹ ń jẹ́ kí a mọ̀ ọ́n.+ Iṣẹ́ ọwọ́ ẹni burúkú ti dẹkùn mú òun fúnra rẹ̀.+ Hígáíónì.* (Sélà) י [Yódì] 17  Àwọn èèyàn burúkú á sá pa dà, wọ́n á sì forí lé Isà Òkú,*Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tó gbàgbé Ọlọ́run. 18  Àmọ́, a kò ní gbàgbé àwọn aláìní títí lọ;+Bẹ́ẹ̀ ni ìrètí àwọn oníwà pẹ̀lẹ́ kò ní já sí asán láé.+ כ [Káfì] 19  Dìde, Jèhófà! Má ṣe jẹ́ kí ẹni kíkú borí. Jẹ́ kí àwọn orílẹ̀-èdè gba ìdájọ́ níwájú rẹ.+  20  Dẹ́rù bà wọ́n, Jèhófà,+Jẹ́ kí àwọn orílẹ̀-èdè mọ̀ pé ẹni kíkú lásán ni wọ́n. (Sélà)

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “kọ orin sí.”
Tàbí “ilẹ̀ tó ń méso jáde.”
Tàbí “ibi gíga tó láàbò.”
Tàbí “Ṣìọ́ọ̀lù,” ìyẹn ibojì aráyé. Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀.