Sáàmù 88:1-18

  • Àdúrà pé kí Ọlọ́run gbani lọ́wọ́ ikú

    • ‘Ẹ̀mí mi ti dé ẹnu Isà Òkú’ (3)

    • ‘Àràárọ̀ ni mò ń gbàdúrà sí ọ’ (13)

Orin. Orin àwọn ọmọ Kórà.+ Sí olùdarí; lọ́nà ti Máhálátì,* kí a kọ ọ́ ní àkọgbà. Másíkílì* ti Hémánì+ tó jẹ́ Ẹ́síráhì. 88  Jèhófà, Ọlọ́run ìgbàlà mi,+Mò ń ké ní ọ̀sán,Mo sì ń wá síwájú rẹ ní òru.+   Jẹ́ kí àdúrà mi wá síwájú rẹ,+Fetí sí* igbe mi fún ìrànlọ́wọ́.+   Nítorí pé wàhálà ti kún ọkàn* mi,+Ẹ̀mí mi sì ti dé ẹnu Isà Òkú.*+   Wọ́n ti kà mí mọ́ àwọn tó ń lọ sínú kòtò;*+Mo ti di ẹni tí kò lè ṣe nǹkan kan,*+   Tí wọ́n fi sílẹ̀ láàárín àwọn òkú,Bí ẹni tí wọ́n pa, tó dùbúlẹ̀ sínú sàréè,Ẹni tí o kò rántí mọ́,Tí kò sì sí lábẹ́ àbójútó* rẹ mọ́.   O ti fi mí sínú kòtò tó jìn jù lọ,Ní ibi tó ṣókùnkùn, nínú ọ̀gbun ńlá tí kò nísàlẹ̀.   Ìrunú rẹ pọ̀ lórí mi,+O sì fi ìgbì rẹ tó ń pariwo bò mí mọ́lẹ̀. (Sélà)   O ti lé àwọn ojúlùmọ̀ mi jìnnà réré sí mi;+O ti sọ mí di ohun ìríra sí wọn. Mo ti kó sí pańpẹ́, mi ò sì lè jáde.   Ojú mi ti di bàìbàì nítorí ìyà tó ń jẹ mí.+ Mo ké pè ọ́, Jèhófà, láti àárọ̀ ṣúlẹ̀;+Ìwọ ni mo tẹ́wọ́ àdúrà sí. 10  Ṣé àwọn òkú lo máa ṣe iṣẹ́ àgbàyanu hàn? Ṣé àwọn tí ikú ti pa* lè dìde wá yìn ọ́?+ (Sélà) 11  Ṣé a lè kéde ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ nínú sàréèTàbí òtítọ́ rẹ ní ibi ìparun?* 12  Ṣé a lè mọ àwọn iṣẹ́ àgbàyanu rẹ nínú òkùnkùnTàbí òdodo rẹ ní ilẹ̀ àwọn ẹni ìgbàgbé?+ 13  Síbẹ̀, Jèhófà, mò ń ké pè ọ́ fún ìrànlọ́wọ́,+Àràárọ̀ ni àdúrà mi ń wá síwájú rẹ.+ 14  Jèhófà, kí ló dé tí o fi kọ̀ mí* sílẹ̀?+ Kí ló dé tí o fi gbé ojú rẹ pa mọ́ fún mi?+ 15  Láti ìgbà èwe miNi ìyà ti ń jẹ mí, mo sì ti fẹ́rẹ̀ẹ́ kú;+Àwọn àjálù tí o jẹ́ kó dé bá mi ti jẹ́ kí n kú sára. 16  Ìbínú rẹ tó ń jó bí iná bò mí mọ́lẹ̀;+Jìnnìjìnnì láti ọ̀dọ̀ rẹ ti pa mí tán. 17  Wọ́n yí mi ká bí omi láti àárọ̀ ṣúlẹ̀;Wọ́n gba ibi gbogbo yọ sí mi, wọ́n sì ká mi mọ́.* 18  O ti lé àwọn ọ̀rẹ́ mi àti àwọn alábàákẹ́gbẹ́ mi jìnnà réré sí mi;+Òkùnkùn ti di alábàákẹ́gbẹ́ mi.

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “Bẹ̀rẹ̀ kí o sì fetí sí.”
Tàbí “Ṣìọ́ọ̀lù,” ìyẹn ibojì aráyé. Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀.
Tàbí “Mo dà bí ọkùnrin tí kò lágbára.”
Tàbí “sàréè.”
Ní Héb., “ọwọ́.”
Tàbí “ti sọ di aláìlágbára.”
Tàbí “ní Ábádónì.”
Tàbí “ọkàn mi.”
Tàbí kó jẹ́, “lẹ́ẹ̀kan náà.”