Sáàmù 87:1-7

  • Síónì, ìlú Ọlọ́run tòótọ́

    • Àwọn tí a bí ní Síónì (4-6)

Ti àwọn ọmọ Kórà.+ Orin atunilára. Orin. 87  Ìpìlẹ̀ ìlú rẹ̀ wà lórí àwọn òkè mímọ́.+   Jèhófà nífẹ̀ẹ́ àwọn ẹnubodè Síónì  +Ju gbogbo àwọn àgọ́ Jékọ́bù lọ.   Àwọn ohun ológo ni wọ́n ń sọ nípa rẹ, ìwọ ìlú Ọlọ́run tòótọ́.+ (Sélà)   Màá ka Ráhábù+ àti Bábílónì mọ́ àwọn tó mọ̀ mí;*Filísíà àti Tírè nìyí, pẹ̀lú Kúṣì. Àwọn èèyàn á sọ pé: “Ẹni yìí ni a bí níbẹ̀.”   Wọ́n á sọ nípa Síónì pé: “Inú rẹ̀ ni a ti bí wọn lẹ́nì kọ̀ọ̀kan.” Ẹni Gíga Jù Lọ yóò sì fìdí rẹ̀ múlẹ̀ ṣinṣin.   Jèhófà yóò kéde nígbà tó bá ń ṣe àkọsílẹ̀ àwọn èèyàn náà pé: “Ẹni yìí ni a bí níbẹ̀.” (Sélà)   Àwọn akọrin+ àti àwọn tó ń jó ijó àjóyípo+ á sọ pé: “Gbogbo ìsun omi mi wà nínú rẹ.”*+

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “bọlá fún mi.”
Tàbí “Ní tèmi, ìwọ ni orísun ohun gbogbo.”