Sáàmù 81:1-16
Sí olùdarí; lórí Gítítì.* Ti Ásáfù.+
81 Ẹ kígbe ayọ̀ sí Ọlọ́run tó jẹ́ agbára wa.+
Ẹ kígbe ìṣẹ́gun sí Ọlọ́run Jékọ́bù.
2 Ẹ bẹ̀rẹ̀ orin, ẹ gbé ìlù tanboríìnì,Háàpù tó ń dún dáadáa àti ohun ìkọrin olókùn tín-ín-rín.
3 Ẹ fun ìwo nígbà òṣùpá tuntun,+Nígbà òṣùpá àrànmọ́jú, nítorí ọjọ́ àjọyọ̀ wa.+
4 Nítorí pé òfin ló jẹ́ fún Ísírẹ́lì,Àṣẹ Ọlọ́run Jékọ́bù.+
5 Ó fi í ṣe ìrántí fún Jósẹ́fù+Nígbà tí Ó jáde lọ láti dojú kọ ilẹ̀ Íjíbítì.+
Mo gbọ́ ohùn* kan tí mi ò mọ̀, tó sọ pé:
6 “Mo gbé ẹrù kúrò ní èjìká rẹ̀;+Mo gba apẹ̀rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ rẹ̀.
7 O pè mí nínú wàhálà tó bá ọ, mo sì gbà ọ́ sílẹ̀;+Mo dá ọ lóhùn láti ojú ọ̀run tó ń sán ààrá.*+
Mo dán ọ wò níbi omi Mẹ́ríbà.*+ (Sélà)
8 Ẹ gbọ́, ẹ̀yin èèyàn mi, màá ta kò yín.
Ìwọ Ísírẹ́lì, ká ní o lè fetí sí mi.+
9 Kò ní sí ọlọ́run àjèjì láàárín rẹ,O kò sì ní forí balẹ̀ fún ọlọ́run ilẹ̀ òkèèrè.+
10 Èmi, Jèhófà, ni Ọlọ́run rẹ,Ẹni tó mú ọ jáde kúrò ní ilẹ̀ Íjíbítì.+
La gbogbo ẹnu rẹ, màá sì fi oúnjẹ kún un.+
11 Àmọ́ àwọn èèyàn mi ò fetí sí ohùn mi;Ísírẹ́lì kò ṣègbọràn sí mi.+
12 Torí náà, mo jẹ́ kí wọ́n máa ṣe ohun tí agídí ọkàn wọn sọ;Wọ́n ń ṣe ohun tí wọ́n rò pé ó tọ́.*+
13 Ká ní àwọn èèyàn mi lè fetí sí mi,+Ká ní Ísírẹ́lì lè rìn ní àwọn ọ̀nà mi!+
14 Kíákíá ni mi ò bá ṣẹ́gun àwọn ọ̀tá wọn;Mi ò bá yí ọwọ́ mi pa dà sí àwọn elénìní wọn.+
15 Àwọn tó kórìíra Jèhófà yóò ba búrúbúrú níwájú rẹ̀,Ohun tó máa ṣẹlẹ̀ sí wọn* yóò sì wà títí láé.
16 Àmọ́ yóò fi àlìkámà* tó dára jù lọ* bọ́ ọ,*+Yóò sì fi oyin inú àpáta tẹ́ ọ lọ́rùn.”+

