Sáàmù 77:1-20

  • Àdúrà lásìkò wàhálà

    • Ṣíṣe àṣàrò lórí àwọn iṣẹ́ Ọlọ́run (11, 12)

    • ‘Ìwọ Ọlọ́run, ta ló tóbi bí rẹ?’ (13)

Sí olùdarí; lórí Jédútúnì.*+ Ti Ásáfù. Orin. 77  Màá fi ohùn mi ké pe Ọlọ́run;Màá ké pe Ọlọ́run, yóò sì gbọ́ mi.+   Ní ọjọ́ wàhálà mi, mo wá Jèhófà.+ Ní òru, mi ò dẹ́kun* títẹ́wọ́ àdúrà sí i. Síbẹ̀, mi* ò gba ìtùnú.   Nígbà tí mo rántí Ọlọ́run, mo kérora;+Ìdààmú bá mi, mi ò sì lágbára mọ́.*+ (Sélà)   Ìwọ mú kí ojú mi là sílẹ̀;Wàhálà bá mi, mi ò sì lè sọ̀rọ̀.   Mo rántí ìgbà àtijọ́,+Àwọn ọdún tó ti kọjá tipẹ́tipẹ́.   Ní òru, mo rántí orin mi;*+Mo ṣàṣàrò nínú ọkàn mi;+Mo* fara balẹ̀ ṣèwádìí.   Ṣé títí láé ni Jèhófà máa ta wá nù ni?+ Ṣé kò ní ṣojú rere sí wa mọ́ láé ni?+   Ṣé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ ti dáwọ́ dúró títí ayé ni? Ṣé ìlérí rẹ̀ máa já sí asán fún gbogbo ìran ni?   Ṣé Ọlọ́run ti gbàgbé láti ṣojú rere ni,+Àbí, ṣé ìbínú rẹ̀ ti dínà àánú rẹ̀ ni? (Sélà) 10  Ṣé ó yẹ kí n máa sọ ní gbogbo ìgbà pé: “Ohun tó ń kó ìdààmú bá* mi ni pé:+ Ẹni Gíga Jù Lọ ti kọ ẹ̀yìn* sí wa”? 11  Màá rántí àwọn iṣẹ́ Jáà;Màá rántí àwọn iṣẹ́ àgbàyanu tí o ti ṣe tipẹ́tipẹ́. 12  Màá ṣe àṣàrò lórí gbogbo iṣẹ́ rẹ,Màá sì ronú jinlẹ̀ nípa àwọn ohun tí o ṣe.+ 13  Ọlọ́run, àwọn ọ̀nà rẹ jẹ́ mímọ́. Ìwọ Ọlọ́run, ọlọ́run wo ló tóbi bí rẹ?+ 14  Ìwọ ni Ọlọ́run tòótọ́, tó ń ṣe àwọn ohun àgbàyanu.+ O ti fi agbára rẹ han àwọn èèyàn.+ 15  O fi agbára* rẹ gba àwọn èèyàn rẹ sílẹ̀,*+Àwọn ọmọ Jékọ́bù àti ti Jósẹ́fù. (Sélà) 16  Omi rí ọ, ìwọ Ọlọ́run;Omi rí ọ, ó sì dà rú.+ Ibú omi ru gùdù. 17  Àwọsánmà da omi sílẹ̀. Ojú ọ̀run tó ṣú dẹ̀dẹ̀ sán ààrá,Àwọn ọfà rẹ sì ń fò síbí sọ́hùn-ún.+ 18  Ìró ààrá rẹ+ dà bí ìró àgbá kẹ̀kẹ́ ẹṣin;Mànàmáná tó ń kọ mú kí ilẹ̀ ayé tí à ń gbé* mọ́lẹ̀;+Ayé mì tìtì, ó sì mì jìgìjìgì.+ 19  Ọ̀nà rẹ gba inú òkun kọjá,+Ipa ọ̀nà rẹ sì gba inú omi púpọ̀ kọjá;Àmọ́ a kò lè rí ipa ẹsẹ̀ rẹ. 20  O darí àwọn èèyàn rẹ bí agbo ẹran,+Lábẹ́ àbójútó* Mósè àti Áárónì.+

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Ní Héb., “ọwọ́ mi ò kú tipiri.”
Tàbí “ọkàn mi.”
Ní Héb., “ẹ̀mí mi dá kú.”
Tàbí “orin tí mo fi ohun ìkọrin olókùn tín-ín-rín kọ.”
Ní Héb., “Ẹ̀mí mi.”
Ní Héb., “yí ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ pa dà.”
Tàbí “tó ń gún.”
Ní Héb., “apá.”
Ní Héb., “ra àwọn èèyàn rẹ pa dà.”
Tàbí “ilẹ̀ tó ń méso jáde.”
Ní Héb., “Nípa ọwọ́.”