Sáàmù 75:1-10

  • Ọlọ́run ń ṣe ìdájọ́ bó ṣe tọ́

    • Àwọn ẹni burúkú yóò mu ohun tó wà nínú ife Jèhófà (8)

Sí olùdarí. Kí a yí i sí orin “Má Ṣe Pa Á Run.” Ti Ásáfù.+ Orin. 75  A fi ọpẹ́ fún ọ, Ọlọ́run, a fi ọpẹ́ fún ọ;Orúkọ rẹ wà nítòsí,+Àwọn èèyàn sì ń kéde àwọn iṣẹ́ àgbàyanu rẹ.   O sọ pé: “Tí mo bá dá àkókò kan,Màá ṣe ìdájọ́ bó ṣe tọ́.   Nígbà tí ayé àti gbogbo àwọn tó ń gbé inú rẹ̀ yọ́,Èmi ni kò jẹ́ kí àwọn òpó rẹ̀ yẹ̀.” (Sélà)   Mo sọ fún àwọn tó ń fọ́nnu pé, “Ẹ má ṣe fọ́nnu,”Mo sì sọ fún àwọn ẹni burúkú pé, “Ẹ má ṣe gbéra ga nítorí agbára* yín.   Ẹ má ṣe gbé ara yín ga sókè nítorí agbára* yínTàbí kí ẹ fi ìgbéraga sọ̀rọ̀.   Nítorí pé kì í ṣeÌlà oòrùn tàbí ìwọ̀ oòrùn tàbí gúúsù ni ìgbéga ti ń wá.   Nítorí Ọlọ́run jẹ́ onídàájọ́.+ Á rẹ ẹnì kan wálẹ̀, á sì gbé ẹlòmíì ga.+   Ife kan wà ní ọwọ́ Jèhófà;+Wáìnì inú rẹ̀ ń ru, wọ́n sì pò ó pọ̀ dáadáa. Ó dájú pé yóò dà á jáde,Gbogbo àwọn ẹni burúkú ayé yóò mu ún tòun ti gẹ̀dẹ̀gẹ́dẹ̀ rẹ̀.”+   Àmọ́ ní tèmi, màá kéde rẹ̀ títí láé;Màá fi orin yin* Ọlọ́run Jékọ́bù. 10  Torí ó sọ pé: “Màá mú gbogbo agbára* ẹni burúkú kúrò,Àmọ́ agbára* olódodo yóò pọ̀ sí i.”

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Ní Héb., “ìwo.”
Ní Héb., “ìwo.”
Tàbí “kọrin sí.”
Ní Héb., “ìwo.”
Ní Héb., “ìwo.”