Sáàmù 74:1-23

  • Àdúrà pé kí Ọlọ́run rántí àwọn èèyàn rẹ̀

    • Onísáàmù sọ àwọn iṣẹ́ ìgbàlà Ọlọ́run (12-17)

    • “Rántí bí ọ̀tá ṣe pẹ̀gàn rẹ” (18)

Másíkílì.* Ti Ásáfù.+ 74  Ọlọ́run, kí ló dé tí o fi kọ̀ wá sílẹ̀ títí láé?+ Kí nìdí tí ìbínú rẹ fi ń jó bí iná* lórí agbo ẹran tó wà ní ibi ìjẹko rẹ?+   Rántí àwọn èèyàn* tí o ti yàn tipẹ́tipẹ́,+Ẹ̀yà tí o rà pa dà láti fi ṣe ogún rẹ.+ Rántí Òkè Síónì, ibi tí o gbé.+   Lọ sí àwọn ibi tó fìgbà gbogbo jẹ́ àwókù.+ Ọ̀tá ti ba gbogbo ohun tó wà ní ibi mímọ́ jẹ́.+   Àwọn ọ̀tá rẹ ń bú ramúramù nínú ibi ìpàdé* rẹ.+ Wọ́n fi àwọn ọ̀págun wọn ṣe àmì síbẹ̀.   Wọ́n dà bí àwọn ọkùnrin tó ń fi àáké dá igbó kìjikìji lu.   Wọ́n fi àáké àti àwọn ọ̀pá onírin fọ́ àwọn iṣẹ́ ọnà ara rẹ̀.+   Wọ́n sọ iná sí ibi mímọ́ rẹ.+ Wọ́n sọ àgọ́ ìjọsìn tí o fi orúkọ rẹ pè di aláìmọ́, wọ́n sì wó o lulẹ̀.   Àwọn àti àwọn ọmọ wọn sọ nínú ọkàn wọn pé: “Gbogbo ibi ìpàdé tó jẹ́ ti Ọlọ́run* ní ilẹ̀ náà la máa dáná sun.”   Kò sí àmì kankan tí a rí;Kò sí wòlíì kankan mọ́,Kò sì sí ẹnì kankan nínú wa tó mọ bí èyí ṣe máa pẹ́ tó. 10  Ọlọ́run, ìgbà wo ni elénìní máa pẹ̀gàn rẹ dà?+ Ṣé ọ̀tá yóò máa hùwà àìlọ́wọ̀ sí orúkọ rẹ títí láé ni?+ 11  Kí ló dé tí o fi fa ọwọ́ rẹ sẹ́yìn, ọwọ́ ọ̀tún rẹ?+ Nà án jáde láti àyà rẹ,* kí o sì pa wọ́n run. 12  Àmọ́, Ọlọ́run ni Ọba mi láti ayébáyé,Ẹni tó ń ṣe àwọn iṣẹ́ ìgbàlà ní ayé.+ 13  O fi agbára rẹ ru òkun sókè;+O fọ́ orí àwọn ẹran ńlá inú òkun. 14  O fọ́ orí Léfíátánì;*O fi ṣe oúnjẹ fún àwọn èèyàn, fún àwọn tó ń gbé aṣálẹ̀. 15  O la ọ̀nà fún àwọn ìsun omi àti odò;+O mú kí àwọn odò tó ń ṣàn nígbà gbogbo gbẹ táútáú.+ 16  Tìrẹ ni ọ̀sán, tìrẹ sì ni òru. Ìwọ lo ṣe ìmọ́lẹ̀* àti oòrùn.+ 17  O pa ààlà sí gbogbo ayé;+O ṣe ìgbà ẹ̀ẹ̀rùn àti ìgbà òtútù.+ 18  Jèhófà, rántí bí ọ̀tá ṣe pẹ̀gàn rẹ,Bí àwọn òmùgọ̀ ṣe hùwà àìlọ́wọ̀ sí orúkọ rẹ.+ 19  Má ṣe fi ẹ̀mí* oriri rẹ fún àwọn ẹranko. Ní ti ẹ̀mí àwọn èèyàn rẹ tí ìyà ń jẹ, má ṣe gbàgbé rẹ̀ títí láé. 20  Rántí májẹ̀mú tí o bá wa dá,Nítorí pé àwọn ibi tó ṣókùnkùn ní ayé ti di ibùgbé àwọn oníwà ipá. 21  Kí ẹni tí a ni lára má ṣe yíjú pa dà nítorí ìjákulẹ̀;+Kí aláìní àti tálákà máa yin orúkọ rẹ.+ 22  Dìde, Ọlọ́run, gba ẹjọ́ ara rẹ rò. Rántí bí àwọn òmùgọ̀ ṣe ń pẹ̀gàn rẹ láti àárọ̀ ṣúlẹ̀.+ 23  Má gbàgbé ohun tí àwọn ọ̀tá rẹ ń sọ. Ariwo àwọn tó ń pè ọ́ níjà ń lọ sókè nígbà gbogbo.

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Ní Héb., “rú èéfín.”
Ní Héb., “àpéjọ rẹ.”
Tàbí “àpéjọ.”
Tàbí “Gbogbo ibi tí wọ́n ti ń sin Ọlọ́run.”
Tàbí “láti ibi tó ṣẹ́ po lára aṣọ rẹ.”
Tàbí “orísun ìmọ́lẹ̀.”
Tàbí “ọkàn.”