Sáàmù 73:1-28

  • Ọkùnrin kan tó bẹ̀rù Ọlọ́run pa dà ní èrò tó bá ti Ọlọ́run mu

    • “Ẹsẹ̀ mi fẹ́rẹ̀ẹ́ yà kúrò lójú ọ̀nà” (2)

    • “Ìdààmú bá mi láti àárọ̀ ṣúlẹ̀” (14)

    • ‘Títí mo fi wọ ibi mímọ́ Ọlọ́run’ (17)

    • Orí ilẹ̀ tọ́ ń yọ̀ ni àwọn ẹni ibi wà (18)

    • Sísúnmọ́ Ọlọ́run dára (28)

Orin Ásáfù.+ 73  Ní tòótọ́, Ọlọ́run ṣe rere fún Ísírẹ́lì, fún àwọn tí ọkàn wọn mọ́.+   Ní tèmi, ẹsẹ̀ mi fẹ́rẹ̀ẹ́ yà kúrò lójú ọ̀nà;Díẹ̀ ló kù kí ẹsẹ̀ mi yọ̀ tẹ̀rẹ́.+   Nítorí mo jowú àwọn agbéraga*Nígbà tí mo rí àlàáfíà àwọn ẹni burúkú.+   Ikú wọn kì í mú ìrora lọ́wọ́;Ara wọn jí pépé.*+   Ìdààmú tó ń bá àwọn èèyàn yòókù kì í bá wọn,+Ìyà tó sì ń jẹ àwọn èèyàn tó kù kì í jẹ wọ́n.+   Nítorí náà, ìgbéraga ni ìlẹ̀kẹ̀ ọrùn wọn;+Wọ́n gbé ìwà ipá wọ̀ bí aṣọ.   Aásìkí* wọn mú kí ẹ̀rẹ̀kẹ́ wọn yọ;Wọ́n ti ní kọjá ohun tí ọkàn wọn rò.   Wọ́n ń fini ṣẹ̀sín, wọ́n sì ń sọ ohun tó burú.+ Wọ́n ń fi ìgbéraga halẹ̀ mọ́ àwọn èèyàn láti ni wọ́n lára.+   Wọ́n ń sọ̀rọ̀ bíi pé wọ́n ga dé ọ̀run,Ahọ́n wọn sì ń sọ̀rọ̀ ìgbéraga káàkiri ayé. 10  Nítorí náà, àwọn èèyàn rẹ̀* yíjú sọ́dọ̀ wọn,Wọ́n sì mu nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi wọn. 11  Wọ́n ń sọ pé: “Báwo ni Ọlọ́run ṣe fẹ́ mọ̀?+ Ṣé Ẹni Gíga Jù Lọ mọ ohun tó ń ṣẹlẹ̀ ni?” 12  Bí ọ̀rọ̀ àwọn ẹni burúkú ṣe rí nìyí, àwọn tí gbogbo nǹkan dẹrùn fún.+ Wọ́n ń kó ọrọ̀ jọ ṣáá.+ 13  Ó dájú pé lásán ni mo pa ọkàn mi mọ́,Tí mo sì wẹ ọwọ́ mi mọ́ pé mo jẹ́ aláìmọwọ́mẹsẹ̀.+ 14  Ìdààmú bá mi láti àárọ̀ ṣúlẹ̀;+Àràárọ̀ ni mò ń gba ìbáwí.+ 15  Ká ní mo ti sọ irú ọ̀rọ̀ yìí ni,Mi ò bá ti dalẹ̀ àwọn èèyàn* rẹ. 16  Nígbà tí mo sapá láti lóye rẹ̀,Ó dà mí láàmú 17  Títí mo fi wọ ibi mímọ́ títóbi lọ́lá ti Ọlọ́run,Tí mo sì wá mọ ọjọ́ ọ̀la wọn. 18  Ó dájú pé orí ilẹ̀ tó ń yọ̀ lo gbé wọn lé.+ Kí wọ́n lè ṣubú kí wọ́n sì pa run.+ 19  Ẹ wo bí wọ́n ti pa rẹ́ lójijì!+ Ẹ wo bí òpin ṣe dé bá wọn lójijì, tí wọ́n sì pa run! 20  Jèhófà, ńṣe ló dà bí àlá nígbà téèyàn bá jí,Nígbà tí o bá dìde, wàá gbé wọn kúrò lọ́kàn.* 21  Àmọ́ ọkàn mi korò,+Inú mi lọ́hùn-ún* sì ń ro mí gógó. 22  Mi ò nírònú, mi ò sì lóye;Mo dà bí ẹranko tí kò ní làákàyè níwájú rẹ. 23  Àmọ́ ní báyìí, ọ̀dọ̀ rẹ ni mo wà nígbà gbogbo;O ti di ọwọ́ ọ̀tún mi mú.+ 24  O fi ìmọ̀ràn rẹ ṣamọ̀nà mi,+Lẹ́yìn náà, wàá mú mi wọnú ògo.+ 25  Ta ni mo ní lọ́run? Lẹ́yìn rẹ, kò sí ohun míì tó wù mí ní ayé.+ 26  Àárẹ̀ lè mú ara mi àti ọkàn mi,Àmọ́ Ọlọ́run ni àpáta ọkàn mi àti ìpín mi títí láé.+ 27  Ní tòótọ́, àwọn tó jìnnà sí ọ yóò ṣègbé. Gbogbo àwọn tó fi ọ́ sílẹ̀ lọ ṣe ìṣekúṣe* ni wàá pa run.*+ 28  Àmọ́ ní tèmi, sísúnmọ́ Ọlọ́run dára fún mi.+ Mo ti fi Jèhófà Olúwa Ọba Aláṣẹ ṣe ibi ààbò mi,Kí n lè máa kéde gbogbo iṣẹ́ rẹ̀.+

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “àwọn tó ń fọ́nnu.”
Tàbí “Ikùn wọn tóbi bẹ̀ǹbẹ̀.”
Ní Héb., “Ọ̀rá.”
Ìyẹn, àwọn èèyàn Ọlọ́run.
Ní Héb., “ìran àwọn ọmọ.”
Ní Héb., “fojú àbùkù wò wọ́n.”
Ní Héb., “Kíndìnrín mi.”
Tàbí “lọ hùwà àìṣòótọ́.”
Ní Héb., “pa lẹ́nu mọ́.”