Sáàmù 71:1-24

  • Ìgbọ́kànlé àwọn arúgbó

    • Ó gbẹ́kẹ̀ lé Ọlọ́run láti ìgbà èwe wá (5)

    • “Nígbà tí mi ò bá lágbára mọ́” (9)

    • ‘Ọlọ́run ti kọ́ mi láti ìgbà èwe mi wá’ (17)

71  Jèhófà, ìwọ ni mo fi ṣe ibi ààbò. Má ṣe jẹ́ kí ojú tì mí láé.+   Gbà mí sílẹ̀, kí o sì gbà mí là nínú òdodo rẹ. Tẹ́tí sí mi,* kí o sì gbà mí sílẹ̀.+   Di àpáta ààbò fún miKí n lè máa ríbi wọ̀ nígbà gbogbo. Pàṣẹ láti gbà mí là,Nítorí ìwọ ni àpáta mi àti ibi ààbò mi.+   Ọlọ́run mi, gbà mí lọ́wọ́ ẹni burúkú,+Gbà mí lọ́wọ́ àwọn tó ń ni èèyàn lára láìtọ́.   Nítorí ìwọ ni ìrètí mi, Jèhófà Olúwa Ọba Aláṣẹ;Ìwọ ni mo gbẹ́kẹ̀ lé* láti ìgbà èwe mi wá.+   Ìwọ ni mo gbára lé láti ìgbà tí wọ́n ti bí mi;Ìwọ ló gbé mi jáde látinú ìyá mi.+ Gbogbo ìgbà ni mò ń yìn ọ́.   Mo dà bí iṣẹ́ ìyanu lójú ọ̀pọ̀ èèyàn,Àmọ́ ìwọ ni ibi ààbò mi tó lágbára.   Ìyìn rẹ kún ẹnu mi;+Mò ń sọ nípa ọlá ńlá rẹ láti àárọ̀ ṣúlẹ̀.   Má ṣe gbé mi sọ nù ní ọjọ́ ogbó mi;+Má pa mí tì nígbà tí mi ò bá lágbára mọ́.+ 10  Àwọn ọ̀tá mi ń sọ̀rọ̀ tí kò dáa sí mi,Àwọn tó sì fẹ́ gba ẹ̀mí* mi gbìmọ̀ pọ̀,+ 11  Wọ́n ń sọ pé: “Ọlọ́run ti pa á tì. Ẹ lé e, kí ẹ sì mú un, torí kò sẹ́ni tó máa gbà á sílẹ̀.”+ 12  Ọlọ́run, má jìnnà sí mi. Ìwọ Ọlọ́run mi, tètè wá ràn mí lọ́wọ́.+ 13  Kí ojú ti àwọn tó ń ta kò mí,*Kí wọ́n sì ṣègbé.+ Ní ti àwọn tó ń wá àjálù mi,Kí ìtìjú àti ẹ̀tẹ́ bò wọ́n mọ́lẹ̀.+ 14  Àmọ́ ní tèmi, èmi yóò máa dúró dè ọ́;Màá fi kún ìyìn rẹ. 15  Ẹnu mi yóò máa ròyìn òdodo rẹ+Àti àwọn iṣẹ́ ìgbàlà rẹ láti àárọ̀ ṣúlẹ̀,Bó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n pọ̀ ju ohun tí mo lè lóye* lọ.+ 16  Màá wá sọ nípa àwọn iṣẹ́ ńlá rẹ,Jèhófà Olúwa Ọba Aláṣẹ;Màá mẹ́nu kan òdodo rẹ, tìrẹ nìkan. 17  Ọlọ́run, o ti kọ́ mi láti ìgbà èwe mi wá,+Títí di báyìí, mò ń kéde àwọn iṣẹ́ àgbàyanu rẹ.+ 18  Kódà tí mo bá darúgbó, tí mo sì hu ewú, Ọlọ́run, má fi mí sílẹ̀.+ Jẹ́ kí n lè sọ nípa agbára* rẹ fún ìràn tó ń bọ̀,Kí n sì sọ nípa agbára ńlá rẹ fún gbogbo àwọn tó ń bọ̀.+ 19  Ọlọ́run, òdodo rẹ ga dé òkè;+O ti ṣe àwọn ohun ńlá;Ọlọ́run, ta ló dà bí rẹ?+ 20  Bó tilẹ̀ jẹ́ pé o ti mú kí n rí ọ̀pọ̀ wàhálà àti àjálù,+Mú kí n sọ jí lẹ́ẹ̀kan sí i;Gbé mi dìde láti inú kòtò* ilẹ̀ ayé.+ 21  Jẹ́ kí ọlá mi pọ̀ sí i,Rọ̀gbà yí mi ká, kí o sì tù mí nínú. 22  Nígbà náà, màá fi ohun ìkọrin olókùn tín-ín-rín yìn ọ́Nítorí òtítọ́ rẹ, Ọlọ́run mi.+ Màá fi háàpù kọ orin ìyìn sí ọ,*Ìwọ Ẹni Mímọ́ Ísírẹ́lì. 23  Ètè mi yóò máa kígbe ayọ̀ bí mo ṣe ń kọ orin ìyìn sí ọ,+Nítorí o gba ẹ̀mí mi là.*+ 24  Ahọ́n mi yóò máa sọ nípa* òdodo rẹ láti àárọ̀ ṣúlẹ̀,+Ojú yóò ti àwọn tó ń wá ìparun mi, wọ́n á sì tẹ́.+

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “Bẹ̀rẹ̀ kí o sì fetí sí mi.”
Tàbí “ìgbọ́kànlé mi.”
Tàbí “ọkàn.”
Tàbí “ta ko ọkàn mi.”
Tàbí “kà.”
Ní Héb., “apá.”
Tàbí “ibú omi.”
Tàbí “fi háàpù kọrin sí ọ.”
Tàbí “o ti ra ọkàn mi pa dà.”
Tàbí “ṣe àṣàrò lórí.”