Sáàmù 65:1-13

  • Ọlọ́run ń bójú tó ayé

    • “Olùgbọ́ àdúrà” (2)

    • “Aláyọ̀ ni ẹni tí o yàn” (4)

    • Oore Ọlọ́run pọ̀ rẹpẹtẹ (11)

Sí olùdarí. Orin Dáfídì. Orin. 65  Ọlọ́run, ìyìn ń dúró dè ọ́ ní Síónì;+A ó san ẹ̀jẹ́ wa fún ọ.+   Ìwọ Olùgbọ́ àdúrà, ọ̀dọ̀ rẹ ni onírúurú èèyàn* yóò wá.+   Àwọn àṣìṣe mi ti bò mí mọ́lẹ̀,+Àmọ́, o dárí àwọn ìṣìnà wa jì wá.+   Aláyọ̀ ni ẹni tí o yàn, tí o sì mú wá sọ́dọ̀ rẹKí ó lè máa gbé inú àwọn àgbàlá rẹ.+ Àwọn ohun rere inú ilé rẹ yóò tẹ́ wa lọ́rùn,+Ìyẹn àwọn ohun inú tẹ́ńpìlì mímọ́* rẹ.+   Wàá fi àwọn iṣẹ́ òdodo tó jẹ́ àgbàyanu dá wa lóhùn,+Ìwọ Ọlọ́run ìgbàlà wa;Ìwọ ni Ìgbẹ́kẹ̀lé gbogbo ayé+Àti ti àwọn tó jìnnà réré lórí òkun.   O* fìdí àwọn òkè múlẹ̀ ṣinṣin nípasẹ̀ agbára rẹ;O* gbé agbára ńlá wọ̀ bí aṣọ.+   O* mú kí àwọn òkun tó ń ru gùdù rọlẹ̀+Pẹ̀lú ariwo ìgbì wọn àti rúkèrúdò àwọn orílẹ̀-èdè.+   Àwọn iṣẹ́ àmì rẹ yóò mú kí ẹ̀rù rẹ ba àwọn tó ń gbé ibi tó jìnnà;+Wàá mú kí àwọn tó wà ní ìlà oòrùn títí dé ìwọ̀ oòrùn kígbe ayọ̀.   Ò ń bójú tó ayé,O mú kí ó ní ọ̀pọ̀ rẹpẹtẹ èso,* kí ilẹ̀ rẹ̀ sì lọ́ràá dáadáa.+ Omi kún inú odò Ọlọ́run;O pèsè oúnjẹ* fún wọn,+Nítorí bí o ṣe ṣètò ayé nìyẹn. 10  O fi omi rin àwọn poro* rẹ̀, o sì mú kí ilẹ̀ rẹ̀ tí a tú* tẹ́jú;O fi ọ̀wààrà òjò mú un dẹ̀; o mú kí ọ̀gbìn rẹ̀ dàgbà.+ 11  O fi oore rẹ dé ọdún ládé;Àwọn ohun rere kún ojú ọ̀nà rẹ rẹpẹtẹ.*+ 12  Àwọn ibi ìjẹko tó wà ní aginjù kún,*+Àwọn òkè kéékèèké gbé ìdùnnú wọ̀ bí aṣọ.+ 13  Àwọn agbo ẹran bo ibi ìjẹko,Ọkà sì bo àwọn àfonífojì.*+ Wọ́n ń kígbe ìṣẹ́gun, bẹ́ẹ̀ ni, wọ́n ń kọrin.+

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Ní Héb., “gbogbo ẹlẹ́ran ara.”
Tàbí “ibi mímọ́.”
Ní Héb., “Ó.”
Ní Héb., “Ó.”
Ní Héb., “Ó.”
Ní Héb., “kí ó kún àkúnwọ́sílẹ̀.”
Ní Héb., “ọkà.”
Tàbí “ebè rẹ̀ tí a kọ.”
Ìyẹn, àárín ebè.
Ní Héb., “Ọ̀rá ń kán tótó ní ojú ọ̀nà rẹ.”
Ní Héb., “ń kán tótó.”
Tàbí “pẹ̀tẹ́lẹ̀.”