Sáàmù 63:1-11

  • Ó ń wù mí láti rí Ọlọ́run

    • “Ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ sàn ju ìyè” (3)

    • ‘Ìpín tó dára jù lọ la fi tẹ́ mi lọ́rùn’ (5)

    • Mò ń ṣe àṣàrò nípa Ọlọ́run ní òru (6)

    • ‘Mo rọ̀ mọ́ Ọlọ́run’ (8)

Orin Dáfídì, nígbà tó wà ní aginjù Júdà.+ 63  Ọlọ́run, ìwọ ni Ọlọ́run mi, mò ń wá ọ.+ Ọkàn mi ń fà sí ọ.*+ Àárẹ̀ ti mú mi* nítorí bó ṣe ń wù mí láti rí ọNí ilẹ̀ tó gbẹ táútáú, níbi tí kò sí omi.+   Torí náà, mo wò ọ́ ní ibi mímọ́;Mo rí agbára rẹ àti ògo rẹ.+   Nítorí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ sàn ju ìyè,+Ètè mi yóò máa yìn ọ́ lógo.+   Torí náà, èmi yóò máa yìn ọ́ ní gbogbo ọjọ́ ayé mi;Èmi yóò máa gbé ọwọ́ mi sókè ní orúkọ rẹ.   Ìpín tó dára jù lọ, tó sì ṣeyebíye jù lọ la fi tẹ́ mi* lọ́rùn,*Torí náà, ẹnu mi yóò yìn ọ́, ètè mi yóò sì kọrin.+   Mo rántí rẹ lórí ibùsùn mi;Mò ń ṣe àṣàrò nípa rẹ nígbà ìṣọ́ òru.+   Nítorí ìwọ ni olùrànlọ́wọ́ mi,+Mo sì ń kígbe ayọ̀ lábẹ́ òjìji ìyẹ́ apá rẹ.+   Mo* rọ̀ mọ́ ọ;Ọwọ́ ọ̀tún rẹ dì mí mú ṣinṣin.+   Àmọ́ àwọn tó fẹ́ gba ẹ̀mí mi*Yóò jìn sínú kòtò ikú. 10  A ó fi wọ́n fún idà,Wọ́n á sì di oúnjẹ fún àwọn ajáko.* 11  Àmọ́ ọba yóò máa yọ̀ nínú Ọlọ́run. Gbogbo ẹni tó ń fi Í búra yóò máa yìn Ín,*Nítorí a ó pa àwọn tó ń parọ́ lẹ́nu mọ́.

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “Òùngbẹ rẹ ń gbẹ mí.”
Ní Héb., “ara mi.”
Ní Héb., “Bí ẹni tó jẹ ọ̀rá, tó sì sanra ni a ṣe tẹ́ mi lọ́rùn.”
Tàbí “ọkàn mi.”
Tàbí “Ọkàn mi.”
Tàbí “ọkàn mi; pa mí.”
Tàbí “kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀.”
Tàbí “ṣògo.”