Sáàmù 60:1-12

  • Ọlọ́run ń ṣẹ́gun àwọn ọ̀tá

    • Asán ni ìgbàlà látọwọ́ èèyàn (11)

    • “Ọlọ́run ló máa fún wa lágbára” (12)

Sí olùdarí; kí a yí i sí “Òdòdó Lílì Ìránnilétí.” Míkítámù.* Ti Dáfídì. Fún kíkọ́ni. Nígbà tó bá Aramu-náháráímù àti Aramu-Sóbà jà, tí Jóábù sì pa dà lọ pa 12,000 àwọn ọmọ Édómù ní Àfonífojì Iyọ̀.+ 60  Ọlọ́run, o ti pa wá tì; o ti ya ààbò wa lulẹ̀.+ O bínú sí wa; àmọ́ ní báyìí, gbà wá pa dà!   O mú kí ilẹ̀ ayé mì tìtì; o mú kí ó lanu. Dí àwọn àlàfo rẹ̀, torí ó ti ń wó.   O mú kí ìyà jẹ àwọn èèyàn rẹ. O mú kí a mu wáìnì tó ń mú wa ta gbọ̀n-ọ́n gbọ̀n-ọ́n.+   Fún* àwọn tó bẹ̀rù rẹ ní àmìKí wọ́n lè sá, kí wọ́n sì yẹ ọfà.* (Sélà)   Kí a lè gba àwọn olùfẹ́ rẹ sílẹ̀,Fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ gbà wá sílẹ̀, kí o sì dá wa lóhùn.+   Ọlọ́run ti sọ̀rọ̀ nínú ìjẹ́mímọ́* rẹ̀ pé: “Màá yọ ayọ̀ ìṣẹ́gun, màá fi Ṣékémù ṣe ogún fún àwọn èèyàn mi,+Màá sì díwọ̀n Àfonífojì* Súkótù fún ẹni tí mo bá fẹ́.+   Gílíádì jẹ́ tèmi, bí Mánásè ṣe jẹ́ tèmi,+Éfúrémù sì ni akoto* orí mi;Júdà ni ọ̀pá àṣẹ mi.+   Móábù ni bàsíà tí mo fi ń wẹ ẹsẹ̀.+ Orí Édómù ni màá ju bàtà mi sí.+ Màá kígbe ìṣẹ́gun lórí Filísíà.”+   Ta ló máa mú mi wá sí ìlú tí a dó tì?* Ta ló máa mú mi lọ sí Édómù?+ 10  Ìwọ Ọlọ́run tí o ti kọ̀ wá sílẹ̀ náà ni,Ìwọ Ọlọ́run wa, tí o kò bá àwọn ọmọ ogun wa jáde mọ́.+ 11  Ràn wá lọ́wọ́ nínú wàhálà wa,Nítorí asán ni ìgbàlà látọwọ́ èèyàn.+ 12  Ọlọ́run ló máa fún wa lágbára,+Yóò sì tẹ àwọn ọ̀tá wa rẹ́.+

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí kó jẹ́, “O ti fún.”
Ní Héb., “ọrun.”
Tàbí “Pẹ̀tẹ́lẹ̀.”
Tàbí kó jẹ́, “ibi mímọ́.”
Irú èyí tí àwọn ọmọ ogun máa ń dé. Ní Héb., “odi agbára.”
Tàbí kó jẹ́, “ìlú olódi.”