Sáàmù 5:1-12

  • Jèhófà ni ibi ààbò àwọn olódodo

    • Ọlọ́run kórìíra ìwà burúkú (4, 5)

    • “Ṣamọ̀nà mi nínú òdodo rẹ” (8)

Sí olùdarí fún Néhílótì.* Orin Dáfídì. 5  Fetí sí ọ̀rọ̀ mi, Jèhófà;+Fiyè sí ẹ̀dùn ọkàn mi.   Fetí sí igbe ìrànlọ́wọ́ mi,Ìwọ Ọba mi àti Ọlọ́run mi, torí pé ìwọ ni mò ń gbàdúrà sí.   Ní òwúrọ̀, Jèhófà, wàá gbọ́ ohùn mi;+Ní òwúrọ̀, màá sọ ohun tó ń jẹ mí lọ́kàn fún ọ,+ màá sì dúró dè ọ́.   Nítorí ìwọ kì í ṣe Ọlọ́run tó fẹ́ràn ìwà burúkú;+Kò sí ẹni burúkú tó lè dúró lọ́dọ̀ rẹ.+   Kò sí agbéraga tó lè dúró níwájú rẹ. O kórìíra gbogbo àwọn tó ń hùwà ibi;+   Wàá pa àwọn tó ń parọ́ run.+ Jèhófà kórìíra àwọn tó ń hu ìwà ipá àti ìwà ẹ̀tàn.*+   Àmọ́ màá wá sínú ilé rẹ+ nítorí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ tó lágbára;+Màá forí balẹ̀ ní ìdojúkọ tẹ́ńpìlì mímọ́* rẹ nínú ẹ̀rù tí mo ní fún ọ.+   Jèhófà, ṣamọ̀nà mi nínú òdodo rẹ nítorí àwọn ọ̀tá mi;Mú kí ọ̀nà rẹ là fún mi.+   Nítorí kò sí èyí tó ṣeé gbára lé nínú ọ̀rọ̀ wọn;Èrò ibi ló kún inú wọn;Sàréè tó ṣí sílẹ̀ ni ọ̀fun wọn;Wọ́n ń fi ẹnu wọn pọ́nni.*+ 10  Àmọ́ Ọlọ́run á dá wọn lẹ́bi;Èrò ibi wọn á mú kí wọ́n ṣubú.+ Kí a lé wọn dà nù torí ẹ̀ṣẹ̀ wọn tó pọ̀ gan-an,Nítorí wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí ọ. 11  Àmọ́ gbogbo àwọn tó fi ọ́ ṣe ibi ààbò á máa yọ̀;+Ìgbà gbogbo ni wọ́n á máa kígbe ayọ̀. Wàá dáàbò bo ọ̀nà àbáwọlé wọn,Àwọn tó nífẹ̀ẹ́ orúkọ rẹ yóò sì máa yọ̀ nínú rẹ. 12  Jèhófà, wàá bù kún ẹni tó bá jẹ́ olódodo;Wàá fi ojú rere dáàbò bò wọ́n bí apata ńlá.+

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “ẹni tó ń ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀ tó sì ń tanni jẹ.”
Tàbí “ibi mímọ́.”
Tàbí “Wọ́n ń lo ahọ́n dídùn.”