Sáàmù 47:1-9

  • Ọlọ́run ni Ọba lórí gbogbo ayé

    • ‘Jèhófà yẹ lẹ́ni tí à ń bẹ̀rù’ (2)

    • Ẹ kọ orin ìyìn sí Ọlọ́run (6, 7)

Sí olùdarí. Ti àwọn ọmọ Kórà.+ Orin. 47  Gbogbo ẹ̀yin èèyàn, ẹ pàtẹ́wọ́. Ẹ fi ayọ̀ kígbe ìṣẹ́gun sí Ọlọ́run.   Nítorí Jèhófà Ẹni Gíga Jù Lọ yẹ lẹ́ni tí à ń bẹ̀rù;+Òun ni Ọba ńlá lórí gbogbo ayé.+   Ó tẹ àwọn èèyàn lórí ba lábẹ́ wa;Ó fi àwọn orílẹ̀-èdè sábẹ́ ẹsẹ̀ wa.+   Ó yan ogún wa fún wa,+Ògo Jékọ́bù, ẹni tó nífẹ̀ẹ́.+ (Sélà)   Ọlọ́run ti gòkè nígbà tí àwọn èèyàn ń kígbe ayọ̀,Jèhófà ti gòkè nígbà tí àwọn èèyàn ń fun ìwo.*   Ẹ kọ orin ìyìn* sí Ọlọ́run, ẹ kọ orin ìyìn. Ẹ kọ orin ìyìn sí Ọba wa, ẹ kọ orin ìyìn.   Nítorí Ọlọ́run ni Ọba gbogbo ayé;+Ẹ kọ orin ìyìn, kí ẹ sì fi ìjìnlẹ̀ òye hàn.   Ọlọ́run ti di Ọba lórí àwọn orílẹ̀-èdè.+ Ọlọ́run jókòó lórí ìtẹ́ mímọ́ rẹ̀.   Àwọn olórí àwọn èèyàn ti kóra jọPẹ̀lú àwọn èèyàn Ọlọ́run Ábúráhámù. Nítorí àwọn alákòóso* ayé jẹ́ ti Ọlọ́run. A ti gbé e ga sókè.+

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “ìwo àgbò; kàkàkí.”
Tàbí “Ẹ kọrin.”
Ní Héb., “àwọn apata.”