Sáàmù 46:1-11
Sí olùdarí. Ti àwọn ọmọ Kórà.+ Lọ́nà ti Álámótì.* Orin.
46 Ọlọ́run ni ibi ààbò wa àti okun wa,+Ìrànlọ́wọ́ tó wà lárọ̀ọ́wọ́tó ní àkókò wàhálà.+
2 Ìdí nìyẹn tí a kò fi ní bẹ̀rù, bí ayé tilẹ̀ ń mì tìtì,Bí àwọn òkè tilẹ̀ ń ṣubú sínú ibú òkun,+
3 Bí omi rẹ̀ tilẹ̀ ń pariwo, tó sì ń ru sókè,*+Bí àwọn òkè tilẹ̀ ń mì jìgìjìgì nítorí ìrugùdù rẹ̀. (Sélà)
4 Odò kan wà tí ṣíṣàn rẹ̀ ń mú kí ìlú Ọlọ́run máa yọ̀,+Àgọ́ ìjọsìn mímọ́ títóbi ti Ẹni Gíga Jù Lọ.
5 Ọlọ́run wà nínú ìlú náà;+ kò ṣeé bì ṣubú.
Ọlọ́run á ràn án lọ́wọ́ tí ilẹ̀ bá mọ́.+
6 Àwọn orílẹ̀-èdè wà nínú rúkèrúdò, àwọn ìjọba ń ṣubú;Ó gbé ohùn rẹ̀ sókè, ayé sì yọ́.+
7 Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun wà pẹ̀lú wa;+Ọlọ́run Jékọ́bù ni ibi ààbò wa.* (Sélà)
8 Ẹ wá wo àwọn iṣẹ́ Jèhófà,Bí ó ṣe gbé àwọn ohun àgbàyanu ṣe ní ayé.
9 Ó ń fòpin sí ogun kárí ayé.+
Ó ṣẹ́ ọrun, ó sì kán ọ̀kọ̀ sí wẹ́wẹ́;Ó sun àwọn kẹ̀kẹ́ ogun* nínú iná.
10 “Ẹ túúbá, kí ẹ sì mọ̀ pé èmi ni Ọlọ́run.
A ó gbé mi ga láàárín àwọn orílẹ̀-èdè;+A ó gbé mi ga ní ayé.”+
11 Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun wà pẹ̀lú wa;+Ọlọ́run Jékọ́bù jẹ́ ibi ààbò fún wa.+ (Sélà)
Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
^ Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀.
^ Tàbí “yọ ìfófòó.”
^ Tàbí “ibi gíga wa tó láàbò.”
^ Tàbí kó jẹ́, “àwọn apata.”

