Sáàmù 45:1-17

  • Ìgbéyàwó ọba tí Ọlọ́run fòróró yàn

    • Ó ní ọ̀rọ̀ rere lẹ́nu (2)

    • “Ọlọ́run ni ìtẹ́ rẹ títí láé” (6)

    • Ọkàn ọba ń fà sí ẹwà ìyàwó rẹ̀ (11)

    • Àwọn ọmọkùnrin yóò jẹ́ olórí ní gbogbo ayé (16)

Sí olùdarí; kí a yí i sí “Òdòdó Lílì.” Ti àwọn ọmọ Kórà.+ Másíkílì.* Orin ìfẹ́. 45  Ohun rere kan ń gbé mi lọ́kàn. Mo sọ pé: “Orin mi dá lórí* ọba kan.”+ Kí ahọ́n mi jẹ́ kálàmù*+ ọ̀jáfáfá adàwékọ.*+   Ìwọ lo rẹwà jù lọ nínú àwọn ọmọ èèyàn. Ọ̀rọ̀ rere ń jáde lẹ́nu rẹ.+ Ìdí nìyẹn tí Ọlọ́run fi bù kún ọ títí láé.+   Sán idà rẹ+ mọ́ ìdí rẹ, ìwọ alágbára ńlá,+Nínú iyì rẹ àti ọlá ńlá rẹ.+   Nínú ọlá ńlá rẹ, kí o ṣẹ́gun;*+Máa gẹṣin lọ nítorí òtítọ́ àti ìrẹ̀lẹ̀ àti òdodo,+Ọwọ́ ọ̀tún rẹ yóò sì ṣe* àwọn ohun àgbàyanu.   Àwọn ọfà rẹ mú, wọ́n ń mú kí àwọn èèyàn ṣubú níwájú rẹ;+Wọ́n ń gún ọkàn àwọn ọ̀tá ọba.+   Ọlọ́run ni ìtẹ́ rẹ títí láé àti láéláé;+Ọ̀pá àṣẹ ìjọba rẹ jẹ́ ọ̀pá àṣẹ ìdúróṣinṣin.*+   O nífẹ̀ẹ́ òdodo,+ o sì kórìíra ìwà burúkú.+ Ìdí nìyẹn tí Ọlọ́run, àní Ọlọ́run rẹ, fi fòróró ayọ̀+ yàn ọ́+ ju àwọn ojúgbà rẹ.   Òjíá àti álóè àti kaṣíà ń já fíkán lára gbogbo aṣọ rẹ;Ìró àwọn ohun ìkọrin olókùn tín-ín-rín látinú ààfin títóbi lọ́lá tí a fi eyín erin ṣe lọ́ṣọ̀ọ́ ń mú inú rẹ dùn.   Àwọn ọmọbìnrin àwọn ọba wà lára àwọn obìnrin ọlọ́lá rẹ. Ayaba* dúró ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ, a fi wúrà Ófírì+ ṣe é lọ́ṣọ̀ọ́. 10  Gbọ́, ìwọ ọmọbìnrin, fiyè sí i, kí o sì fetí sílẹ̀;Gbàgbé àwọn èèyàn rẹ àti ilé bàbá rẹ. 11  Ọkàn ọba yóò máa fà sí ọ nítorí ẹwà rẹ,Torí òun ni olúwa rẹ,Nítorí náà, tẹrí ba fún un. 12  Ọmọbìnrin Tírè máa mú ẹ̀bùn wá;Àwọn tó lọ́rọ̀ jù lọ máa wá ojú rere rẹ.* 13  Nínú ààfin,* ọmọbìnrin ọba gbé ògo wọ̀ bí aṣọ;A fi wúrà ṣe aṣọ rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́.* 14  A ó mú un wá sọ́dọ̀ ọba nínú aṣọ tí a hun dáadáa.* A ó mú àwọn wúńdíá ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ tó ń tẹ̀ lé e wọlé síwájú rẹ. 15  A ó mú wọn wá pẹ̀lú ayọ̀ àti ìdùnnú,Wọ́n á sì wọ ààfin ọba. 16  Àwọn ọmọkùnrin rẹ yóò gba ipò àwọn baba ńlá rẹ. Wàá yàn wọ́n ṣe olórí ní gbogbo ayé.+ 17  Màá jẹ́ kí àwọn èèyàn mọ orúkọ rẹ jálẹ̀ gbogbo ìran tó ń bọ̀.+ Ìdí nìyẹn tí àwọn èèyàn á fi máa yìn ọ́ títí láé àti láéláé.

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “gègé.”
Tàbí “akọ̀wé òfin.”
Ní Héb., “Àwọn iṣẹ́ mi jẹ́ nípa.”
Ní Héb., “kọ́ ọ ní.”
Tàbí “ṣàṣeyọrí.”
Tàbí “ìdájọ́ òdodo.”
Tàbí “Olorì.”
Tàbí “tù ọ́ lójú.”
Ní Héb., “Nínú.”
Ní Héb., “A lẹ àwọn ohun ọ̀ṣọ́ wúrà mọ́ aṣọ rẹ̀.”
Tàbí kó jẹ́, “aṣọ tí a kóṣẹ́ sí lára.”