Sáàmù 39:1-13

  • Ẹ̀mí èèyàn kúrú

    • Èémí lásán ni èèyàn (5, 11)

    • “Má ṣe gbójú fo omijé mi” (12)

Sí olùdarí; ti Jédútúnì.*+ Orin Dáfídì. 39  Mo sọ pé: “Màá ṣọ́ ẹsẹ̀ miKí n má bàa fi ahọ́n mi dẹ́ṣẹ̀.+ Màá fi ìbonu bo ẹnu mi+Ní gbogbo ìgbà tí ẹni burúkú bá wà níwájú mi.”   Mi ò lè sọ̀rọ̀, ṣe ni mo dákẹ́;+Mi ò sọ nǹkan kan, kódà nípa ohun rere,Síbẹ̀, ìrora mi le kọjá sísọ.*   Ọkàn mi rọra ń jó* nínú mi bí iná. Bí mo ṣe ń ronú* ni iná náà ń jó. Ahọ́n mi wá sọ pé:   “Jèhófà, jẹ́ kí n mọ ohun tó máa gbẹ̀yìn miÀti bí ọjọ́ ayé mi ṣe máa gùn tó,+Kí n lè mọ bí ẹ̀mí mi ṣe kúrú tó.*   Lóòótọ́, o ti mú kí ọjọ́ ayé mi kéré;*+Gbogbo ọjọ́ ayé mi kò sì jẹ́ nǹkan kan lójú rẹ.+ Ní ti ọmọ èèyàn, bó tilẹ̀ dà bíi pé kò sí nínú ewu, bí èémí lásán ló rí.+ (Sélà)   Dájúdájú, bí òjìji ni ọmọ èèyàn ń rìn kiri. Ó ń sáré kiri* lórí òfo. Ó ń kó ọrọ̀ jọ pelemọ láìmọ ẹni tó máa gbádùn rẹ̀.+   Kí wá ni kí n máa retí, Jèhófà? Ìwọ nìkan ni ìrètí mi.   Yọ mí nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi.+ Má ṣe jẹ́ kí àwọn òmùgọ̀ sọ mí di ẹni ẹ̀gàn.   Mi ò lè sọ̀rọ̀;Mi ò lè la ẹnu mi,+Nítorí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ ni.+ 10  Mú ìyọnu rẹ kúrò lórí mi. Àárẹ̀ mú mi nítorí ọwọ́ rẹ ti gbá mi. 11  O fi ìyà tọ́ èèyàn sọ́nà nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀;+O run nǹkan tó kà sí iyebíye bí ìgbà tí òólá* bá jẹ nǹkan. Dájúdájú, èémí lásán ni ọmọ èèyàn.+ (Sélà) 12  Gbọ́ àdúrà mi, Jèhófà,Fetí sí igbe mi fún ìrànlọ́wọ́.+ Má ṣe gbójú fo omijé mi. Nítorí àjèjì lásán ni mo jẹ́ sí ọ,+Arìnrìn-àjò tó ń kọjá lọ* ni mí, bíi gbogbo àwọn baba ńlá mi.+ 13  Má ṣe wò mí nínú ìbínú rẹ, kí n lè túra káKí n tó kọjá lọ tí mi ò sì ní sí mọ́.”

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “ru sókè.”
Ní Héb., “ti gbóná.”
Tàbí “ń kẹ́dùn.”
Tàbí “bí ọjọ́ ayé mi ṣe kéré tó.”
Ní Héb., “jẹ́ ìbú ọwọ́.”
Ní Héb., “ń pariwo.”
Tàbí “kòkòrò.”
Tàbí “Olùtẹ̀dó.”