Sáàmù 35:1-28

  • Àdúrà ìdáǹdè kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá

    • Kí a lé àwọn ọ̀tá dà nù (5)

    • Máa yin Ọlọ́run láàárín ọ̀pọ̀lọpọ̀ èèyàn (18)

    • Wọ́n kórìíra mi láìnídìí (19)

Ti Dáfídì. 35  Jèhófà, gbèjà mi níwájú àwọn tó ń ta kò mí;+Dojú ìjà kọ àwọn tó ń bá mi jà.+   Gbé asà* rẹ àti apata ńlá,+Kí o sì dìde láti gbèjà mi.+   Yọ ọ̀kọ̀ rẹ àti àáké ogun* láti dojú kọ àwọn tó ń lépa mi.+ Sọ fún mi* pé: “Èmi ni ìgbàlà rẹ.”+   Kí ìtìjú bá àwọn tó ń dọdẹ ẹ̀mí mi,* kí wọ́n sì tẹ́.+ Kí àwọn tó ń gbèrò láti pa mí sá pa dà nínú ìtìjú.   Kí wọ́n dà bí ìyàngbò* nínú afẹ́fẹ́;Kí áńgẹ́lì Jèhófà lé wọn dà nù.+   Kí ọ̀nà wọn ṣókùnkùn, kí ó sì máa yọ̀ bọ̀rọ́Bí áńgẹ́lì Jèhófà ṣe ń lépa wọn.   Nítorí pé wọ́n ti dẹ àwọ̀n dè mí láìnídìí;Wọ́n ti gbẹ́ kòtò fún mi* láìnídìí.   Kí àjálù dé bá a lójijì;Kí àwọ̀n tí ó dẹ mú òun fúnra rẹ̀;Kí ó kó sínú rẹ̀, kí ó sì pa run.+   Àmọ́ èmi* yóò máa yọ̀ nínú Jèhófà;Èmi yóò máa yọ̀ nínú àwọn iṣẹ́ ìgbàlà rẹ̀. 10  Gbogbo egungun mi á sọ pé: “Jèhófà, ta ló dà bí rẹ? Ò ń gba àwọn tí kò ní olùrànlọ́wọ́ sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn tó lágbára jù wọ́n lọ,+O sì ń gba àwọn tí kò ní olùrànlọ́wọ́ àti tálákà lọ́wọ́ àwọn tó ń jà wọ́n lólè.”+ 11  Àwọn ẹlẹ́rìí èké jáde wá,+Wọ́n ń bi mí ní àwọn ohun tí mi ò mọ̀. 12  Wọ́n ń fi ibi san rere fún mi,+Èyí sì mú kí n* máa ṣọ̀fọ̀. 13  Àmọ́ nígbà tí wọ́n ń ṣàìsàn, mo wọ aṣọ ọ̀fọ̀,*Mo gbààwẹ̀ láti fi pọ́n ara mi* lójú,Nígbà tí àdúrà mi kò sì gbà,* 14  Mò ń rìn kiri, mo sì ń ṣọ̀fọ̀ bí ẹni tí ọ̀rẹ́ rẹ̀ tàbí ọmọ ìyá rẹ̀ kú;Ìbànújẹ́ dorí mi kodò bí ẹni tó ń ṣọ̀fọ̀ ìyá rẹ̀. 15  Àmọ́ nígbà tí mo kọsẹ̀, inú wọn dùn, wọ́n sì kóra jọ;Wọ́n kóra jọ láti pa mí ní ibi tí wọ́n lúgọ sí dè mí;Wọ́n ya mí sí wẹ́wẹ́, wọn ò sì dákẹ́ ọ̀rọ̀ ìbàjẹ́. 16  Àwọn tí kò ṣe ìfẹ́ Ọlọ́run fi mí ṣẹ̀sín,*Wọ́n ń wa eyín wọn pọ̀ sí mi.+ 17  Jèhófà, ìgbà wo lo máa wò mí dà?+ Yọ mí* nínú ogun tí wọ́n gbé tì mí,+Gba ẹ̀mí mi tó ṣeyebíye* lọ́wọ́ àwọn ọmọ kìnnìún.*+ 18  Nígbà náà, èmi yóò máa dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ nínú ìjọ ńlá;+Èmi yóò máa yìn ọ́ láàárín ọ̀pọ̀lọpọ̀ èèyàn. 19  Má ṣe jẹ́ kí àwọn tó sọ ara wọn di ọ̀tá mi láìnídìí yọ̀ mí;Má ṣe jẹ́ kí àwọn tó kórìíra mi láìnídìí+ wò mí tìkà-tẹ̀gbin.+ 20  Nítorí wọn kì í sọ ọ̀rọ̀ àlàáfíà,Ṣe ni wọ́n ń fẹ̀tàn hùmọ̀ ibi sí àwọn èèyàn àlàáfíà ilẹ̀ náà.+  21  Wọ́n lanu gbàù láti fẹ̀sùn kàn mí,Wọ́n sọ pé: “Àháà! Àháà! Ojú wa ti rí i.” 22  O ti rí èyí ná, Jèhófà. Má ṣe dákẹ́.+ Jèhófà, má jìnnà sí mi.+ 23  Dìde, kí o sì wá gbèjà mi,Jèhófà, Ọlọ́run mi, gbèjà mi nínú ẹjọ́ mi. 24  Jèhófà Ọlọ́run mi, ṣe ìdájọ́ mi nítorí òdodo rẹ;+Má ṣe jẹ́ kí wọ́n yọ̀ mí. 25  Kí wọ́n má ṣe sọ fún ara wọn pé: “Àháà! Ọwọ́ wa ti tẹ ohun tí à ń fẹ́!”* Kí wọ́n má ṣe sọ pé: “A ti gbé e mì.”+ 26  Kí ojú ti gbogbo wọn, kí wọ́n sì tẹ́,Àwọn tó ń yọ̀ nítorí àjálù mi. Kí àwọn tó ń gbé ara wọn ga sí mi gbé ìtìjú àti ẹ̀tẹ́ wọ̀ bí aṣọ. 27  Àmọ́ kí àwọn tí inú wọn ń dùn sí òdodo mi kígbe ayọ̀;Kí wọ́n máa sọ nígbà gbogbo pé: “Kí a gbé Jèhófà ga, ẹni tí inú rẹ̀ ń dùn sí àlàáfíà ìránṣẹ́ rẹ̀.”+  28  Nígbà náà, ahọ́n mi yóò máa ròyìn* òdodo rẹ,+Yóò sì máa yìn ọ́ láti àárọ̀ ṣúlẹ̀.+

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Apata kékeré tí àwọn tafàtafà sábà máa ń gbé dání.
Tàbí “àáké olórí méjì.”
Tàbí “ọkàn mi.”
Tàbí “ọkàn mi.”
Ìyẹn, èèpo fúlẹ́fúlẹ́ ara ọkà.
Tàbí “ọkàn mi.”
Tàbí “ọkàn mi.”
Tàbí “ọkàn mi.”
Ní Héb., “aṣọ àpò ìdọ̀họ.”
Tàbí “bá pa dà sí àyà mi.”
Tàbí “ọkàn mi.”
Tàbí kó jẹ́, “Àwọn tí kò ṣe ìfẹ́ Ọlọ́run ń fini ṣẹ̀sín nítorí búrẹ́dì.”
Tàbí “ọkàn mi.”
Ní Héb., “ọ̀kan ṣoṣo mi,” ó ń tọ́ka sí ọkàn rẹ̀ tàbí ẹ̀mí rẹ̀.
Tàbí “ọmọ kìnnìún tó tó ọdẹ ṣe (onígọ̀gọ̀).”
Tàbí “Àháà! Ọkàn wa.”
Tàbí “ṣàṣàrò lórí.”