Sáàmù 30:1-12
-
Ọ̀fọ̀ yí pa dà di ìdùnnú
-
Ojú rere Ọlọ́run wà títí ọjọ́ ayé (5)
-
Orin. Orin ìṣílé. Ti Dáfídì.
30 Màá gbé ọ ga, Jèhófà, nítorí o ti gbé mi* sókè,O ò jẹ́ kí àwọn ọ̀tá mi yọ̀ mí.+
2 Jèhófà Ọlọ́run mi, mo ké pè ọ́ fún ìrànlọ́wọ́, o sì wò mí sàn.+
3 Jèhófà, o ti gbé mi* sókè látinú Isà Òkú.*+
O mú kí n wà láàyè, o ò sì jẹ́ kí n rì sínú kòtò.*+
4 Ẹ fi orin yin* Jèhófà, ẹ̀yin ẹni ìdúróṣinṣin rẹ̀,+Ẹ fi ọpẹ́ fún orúkọ* mímọ́ rẹ̀;+
5 Nítorí ìbínú rẹ̀ lórí èèyàn kì í pẹ́ rárá,+Àmọ́ ojú rere* rẹ̀ sí èèyàn wà títí ọjọ́ ayé.+
Ẹkún lè wà ní àṣálẹ́, àmọ́ tó bá di àárọ̀, igbe ayọ̀ á sọ.+
6 Nígbà tí kò sí ìdààmú kankan fún mi, mo sọ pé:
“Mìmì kan ò ní mì mí.”*
7 Jèhófà, nígbà tí o ṣojú rere sí mi,* o mú kí n lágbára bí òkè.+
Àmọ́ nígbà tí o fi ojú rẹ pa mọ́, jìnnìjìnnì bá mi.+
8 Jèhófà, ìwọ ni mò ń ké pè;+Jèhófà ni mo sì ń bẹ̀ fún ojú rere.
9 Èrè wo ló wà nínú ikú* mi, nínú bí mo ṣe ń lọ sínú kòtò?*+
Ṣé erùpẹ̀ lè yìn ọ́?+ Ṣé ó lè sọ nípa ìṣòtítọ́ rẹ?+
10 Fetí sílẹ̀, Jèhófà, kí o sì ṣojú rere sí mi.+
Jèhófà, wá ràn mí lọ́wọ́.+
11 O ti sọ ọ̀fọ̀ mi di ijó;O ti bọ́ aṣọ ọ̀fọ̀* mi, o sì fi aṣọ ìdùnnú wọ̀ mí,
12 Kí n* lè máa kọrin ìyìn rẹ, kí n má sì dákẹ́.
Jèhófà Ọlọ́run mi, èmi yóò máa yìn ọ́ títí láé.
Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
^ Tàbí “fà mí.”
^ Tàbí “ọkàn mi.”
^ Tàbí “Ṣìọ́ọ̀lù,” ìyẹn ibojì aráyé. Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀.
^ Tàbí “sàréè.”
^ Tàbí “kọrin sí.”
^ Ní Héb., “ìrántí.”
^ Tàbí “inú rere.”
^ Tàbí “Mi ò ní ta gọ̀ọ́gọ̀ọ́ (gbọ̀n-ọ́n gbọ̀n-ọ́n).”
^ Tàbí “fi inú rere hàn sí mi.”
^ Ní Héb., “ẹ̀jẹ̀.”
^ Tàbí “sàréè.”
^ Ní Héb., “aṣọ àpò ìdọ̀họ.”
^ Tàbí “ògo mi.”

