Sáàmù 3:1-8
Orin tí Dáfídì kọ nígbà tó ń sá lọ nítorí Ábúsálómù ọmọ rẹ̀.+
3 Jèhófà, kí nìdí tí àwọn ọ̀tá mi fi pọ̀ tó báyìí?+
Kí nìdí tí ọ̀pọ̀ èèyàn fi ń dìde sí mi?+
2 Ọ̀pọ̀ ń sọ nípa mi* pé:
“Ọlọ́run ò ní gbà á sílẹ̀.”+ (Sélà)*
3 Àmọ́, ìwọ Jèhófà ni apata tó yí mi ká,+Ògo mi+ àti Ẹni tó ń gbé orí mi sókè.+
4 Màá ké pe Jèhófà,Yóò sì dá mi lóhùn láti òkè mímọ́ rẹ̀.+ (Sélà)
5 Màá dùbúlẹ̀, màá sùn;Màá sì jí ní àlàáfíà,Nítorí Jèhófà ń tì mí lẹ́yìn.+
6 Mi ò bẹ̀rù ẹgbẹẹgbẹ̀rún èèyànTí wọ́n yí mi ká láti gbógun tì mí.+
7 Dìde, Jèhófà! Gbà mí sílẹ̀,+ ìwọ Ọlọ́run mi!
Nítorí wàá gbá gbogbo àwọn ọ̀tá mi ní páárì ẹ̀rẹ̀kẹ́;Wàá ká eyín àwọn ẹni burúkú.+
8 Ti Jèhófà ni ìgbàlà.+
Ìbùkún rẹ wà lórí àwọn èèyàn rẹ. (Sélà)

