Sáàmù 29:1-11

  • Ohùn Jèhófà lágbára

    • Jọ́sìn nínú aṣọ ọ̀ṣọ́ mímọ́ (2)

    • “Ọlọ́run ológo sán ààrá” (3)

    • Jèhófà ń fún àwọn èèyàn rẹ̀ ní agbára (11)

Orin Dáfídì. 29  Ẹ fún Jèhófà ní ohun tí ó tọ́ sí i, ẹ̀yin ọmọ àwọn alágbára,Ẹ fún Jèhófà ní ohun tí ó tọ́ sí i nítorí ògo àti agbára rẹ̀.+   Ẹ fún Jèhófà ní ògo tí ó yẹ orúkọ rẹ̀. Ẹ forí balẹ̀ fún* Jèhófà nínú aṣọ ọ̀ṣọ́ mímọ́.*   A gbọ́ ohùn Jèhófà lórí omi;Ọlọ́run ológo sán ààrá.+ Jèhófà wà lórí omi púpọ̀.+   Ohùn Jèhófà ní agbára;+Ohùn Jèhófà ní ọlá ńlá.   Ohùn Jèhófà ń fa àwọn igi kédárì ya;Bẹ́ẹ̀ ni, Jèhófà ń fa àwọn igi kédárì Lẹ́bánónì+ ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ.   Ó ń mú kí Lẹ́bánónì* máa ta pọ́n-ún pọ́n-ún bí ọmọ màlúùÀti Síríónì+ bí akọ ọmọ màlúù igbó.   Ohùn Jèhófà ń mú kí mànàmáná kọ;+   Ohùn Jèhófà ń mú kí aginjù mì tìtì;+Jèhófà ń mú kí aginjù Kádéṣì+ mì tìtì.   Ohùn Jèhófà kó jìnnìjìnnì bá àwọn àgbọ̀nrín, wọ́n sì bímọ,Bákan náà, ó ń tú àwọn igbó kìjikìji sí borokoto.+ Gbogbo àwọn tó wà nínú tẹ́ńpìlì rẹ̀ sì sọ pé: “Ògo!” 10  Jèhófà gúnwà sórí ìkún omi;*+Jèhófà gúnwà bí Ọba títí láé.+ 11  Jèhófà yóò fún àwọn èèyàn rẹ̀ ní agbára.+ Jèhófà yóò fi àlàáfíà jíǹkí àwọn èèyàn rẹ̀.+

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “jọ́sìn.”
Tàbí kó jẹ́, “nítorí ògo ìjẹ́mímọ́ rẹ̀.”
Ó ṣe kedere pé, agbègbè olókè Lẹ́bánónì ló ń sọ.
Tàbí “òkun tó wà ní ọ̀run.”