Sáàmù 26:1-12

  • Rírìn nínú ìwà títọ́

    • “Yẹ̀ mí wò, Jèhófà” (2)

    • Yẹra fún ẹgbẹ́ búburú (4, 5)

    • ‘Màá rìn yí ká pẹpẹ Ọlọ́run’ (6)

Ti Dáfídì. 26  Ṣe ìdájọ́ mi, Jèhófà, nítorí mo ti rìn nínú ìwà títọ́ mi;+Jèhófà ni mo gbẹ́kẹ̀ lé láìmikàn.+   Yẹ̀ mí wò, Jèhófà, kí o sì dán mi wò;Yọ́ èrò inú mi* àti ọkàn mi mọ́.+   Nítorí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ máa ń wà níwájú mi nígbà gbogbo,Mo sì ń rìn nínú òtítọ́ rẹ.+   Èmi kì í bá àwọn ẹlẹ́tàn kẹ́gbẹ́,*+Mo sì máa ń yẹra fún àwọn tó ń fi ẹni tí wọ́n jẹ́ pa mọ́.*   Mo kórìíra àwùjọ àwọn aṣebi,+Mi ò sì jẹ́ bá àwọn ẹni burúkú kẹ́gbẹ́.*+   Màá jẹ́ kí ọwọ́ mi mọ́,Màá sì rìn yí ká pẹpẹ rẹ, Jèhófà,   Láti mú kí a gbọ́ ohùn ọpẹ́+Àti láti kéde gbogbo iṣẹ́ àgbàyanu rẹ.   Jèhófà, mo nífẹ̀ẹ́ ilé tí ò ń gbé,+Ibi tí ògo rẹ wà.+   Má ṣe gbá mi* dà nù pẹ̀lú àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀+Má sì gba ẹ̀mí mi pẹ̀lú àwọn oníwà ipá,* 10  Àwọn tó ń lọ́wọ́ nínú ìwà àìnítìjú,Tí àbẹ̀tẹ́lẹ̀ sì kún ọwọ́ ọ̀tún wọn. 11  Àmọ́ ní tèmi, èmi yóò máa rìn nínú ìwà títọ́ mi. Gbà mí sílẹ̀,* kí o sì ṣojú rere sí mi. 12  Ẹsẹ̀ mi dúró lórí ilẹ̀ tó tẹ́jú;+Nínú ìjọ ńlá,* èmi yóò yin Jèhófà.+

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “inú mi lọ́hùn-ún.” Ní Héb.,“kíndìnrín mi.”
Ní Héb., “jókòó.”
Tàbí “Èmi kì í bá àwọn alágàbàgebè ṣe wọléwọ̀de.”
Ní Héb., “jókòó.”
Tàbí “ọkàn mi.”
Tàbí “àwọn tó ń ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀.”
Ní Héb., “Rà mí pa dà.”
Ní Héb., “àwọn àpéjọ.”