Sáàmù 22:1-31
Sí olùdarí; kí a yí i sí “Egbin Àfẹ̀mọ́jú.”* Orin Dáfídì.
22 Ọlọ́run mi, Ọlọ́run mi, kí ló dé tí o fi kọ̀ mí sílẹ̀?+
Kí nìdí tí o fi jìnnà sí mi láti gbà mí sílẹ̀,Tí o sì jìnnà sí igbe ìrora mi?+
2 Ọlọ́run mi, mò ń ké pè ọ́ ní ọ̀sán, àmọ́ o ò dáhùn;+Kódà ní òru, mi ò dákẹ́.
3 Àmọ́ ẹni mímọ́+ ni ọ́,Ìyìn Ísírẹ́lì sì yí ọ ká.*
4 Ìwọ ni àwọn baba wa gbẹ́kẹ̀ lé;+Wọ́n gbẹ́kẹ̀ lé ọ, o sì ń gbà wọ́n sílẹ̀.+
5 Ìwọ ni wọ́n ké pè, o sì gbà wọ́n;Wọ́n gbẹ́kẹ̀ lé ọ, o ò sì já wọn kulẹ̀.*+
6 Àmọ́ kòkòrò mùkúlú ni mí, èmi kì í ṣe èèyàn,Àwọn èèyàn ń fi mí ṣẹ̀sín,* aráyé ò sì kà mí sí.+
7 Gbogbo àwọn tó ń rí mi ló ń fi mí ṣe yẹ̀yẹ́;+Wọ́n ń yínmú, wọ́n sì ń mi orí wọn, pé:+
8 “Ó fi ara rẹ̀ lé Jèhófà lọ́wọ́. Kí Ó gbà á sílẹ̀ báyìí!
Kí Ó gbà á là, ṣebí ó fẹ́ràn Rẹ̀ gan-an!”+
9 Ìwọ ni Ó gbé mi jáde láti inú ìyá mi,+Ìwọ ni O mú kí ọkàn mi balẹ̀ ní àyà ìyá mi.
10 Ọwọ́ rẹ ni mo wà* látìgbà tí wọ́n ti bí mi;Ìwọ ni Ọlọ́run mi láti inú ìyá mi wá.
11 Má jìnnà sí mi, torí wàhálà ti dé tán+Mi ò sì ní olùrànlọ́wọ́+ míì.
12 Ọ̀pọ̀ akọ ọmọ màlúù yí mi ká;+Àwọn akọ màlúù Báṣánì tó lágbára rọ̀gbà yí mi ká.+
13 Wọ́n ya ẹnu wọn sí mi,+Bíi kìnnìún tó ń ké ramúramù, tó sì ń fa ẹran ya.+
14 A tú mi jáde bí omi;Gbogbo egungun mi ti yẹ̀.
Ọkàn mi ti dà bí ìda;+Ó yọ́ nínú mi lọ́hùn-ún.+
15 Okun mi ti tán, mo dà bí èéfọ́ ìkòkò;+Ahọ́n mi lẹ̀ mọ́ ẹran ìdí eyín mi;+O sì mú mi wálẹ̀ sínú ekuru kí n lè kú.+
16 Nítorí àwọn ajá yí mi ká;+Wọ́n ká mi mọ́ bí ìgbà tí àwọn aṣebi bá káni mọ́,+Wọ́n wà níbi ọwọ́ àti ẹsẹ̀ mi bíi kìnnìún.+
17 Mo lè ka gbogbo egungun mi.+
Wọ́n ń wò mí, wọ́n sì tẹjú mọ́ mi.
18 Wọ́n pín ẹ̀wù mi láàárín ara wọn,Wọ́n sì ṣẹ́ kèké nítorí aṣọ mi.+
19 Àmọ́ ìwọ, Jèhófà, má jìnnà sí mi.+
Ìwọ ni okun mi; tètè wá ràn mí lọ́wọ́.+
20 Gbà mí* lọ́wọ́ idà,Gba ẹ̀mí mi tó ṣeyebíye* lọ́wọ́ èékánná* ajá;+
21 Gbà mí kúrò lẹ́nu kìnnìún + àti lọ́wọ́ ìwo akọ màlúù igbó;Dá mi lóhùn, kí o sì gbà mí sílẹ̀.
22 Màá sọ orúkọ rẹ fún àwọn arákùnrin mi;+Màá sì yìn ọ́ láàárín ìjọ.+
23 Ẹ̀yin tí ẹ bẹ̀rù Jèhófà, ẹ yìn ín!
Gbogbo ẹ̀yin ọmọ* Jékọ́bù, ẹ yìn ín lógo!+
Ẹ máa bẹ̀rù rẹ̀, gbogbo ẹ̀yin ọmọ* Ísírẹ́lì.
24 Nítorí kò gbójú fo ìyà tó ń jẹ ẹni tí ara ń ni, kò sì ṣàìka ìpọ́njú rẹ̀ sí;+Kò gbé ojú rẹ̀ pa mọ́ fún un.+
Nígbà tó ké pè é fún ìrànlọ́wọ́, ó gbọ́.+
25 Màá yìn ọ́ láàárín ìjọ ńlá;+Màá san àwọn ẹ̀jẹ́ mi níwájú àwọn tó bẹ̀rù rẹ.
26 Àwọn oníwà pẹ̀lẹ́ á jẹ, wọ́n á sì yó;+Àwọn tó ń wá Jèhófà yóò yìn ín.+
Kí wọ́n gbádùn ayé* títí láé.
27 Gbogbo ayé á rántí, wọ́n á sì yíjú sọ́dọ̀ Jèhófà.
Gbogbo ìdílé àwọn orílẹ̀-èdè á tẹrí ba níwájú rẹ.+
28 Nítorí pé ti Jèhófà ni ìjọba;+Ó ń ṣàkóso àwọn orílẹ̀-èdè.
29 Gbogbo àwọn tó láásìkí* nínú ayé á jẹ, wọ́n á sì tẹrí ba;Gbogbo àwọn tó ń lọ sínú erùpẹ̀ yóò wólẹ̀ níwájú rẹ̀;Kò sí ìkankan lára wọn tó lè dá ẹ̀mí* rẹ̀ sí.
30 Àwọn àtọmọdọ́mọ wọn* yóò máa sìn ín;Ìran tó ń bọ̀ yóò gbọ́ nípa Jèhófà.
31 Wọ́n á wá, wọ́n á sì sọ nípa òdodo rẹ̀.
Wọ́n á sọ fún àwọn ọmọ tí a máa bí nípa ohun tó ṣe.
Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
^ Ó ṣeé ṣe kó jẹ́ ohùn orin tàbí oríṣi orin kan.
^ Tàbí “O gúnwà láàárín (lórí) ìyìn Ísírẹ́lì.”
^ Tàbí “dójú tì wọ́n.”
^ Tàbí “Ẹni ẹ̀gàn ni mí lójú àwọn èèyàn.”
^ Ní Héb., “ni wọ́n jù mí sí.”
^ Tàbí “Gba ọkàn mi.”
^ Ní Héb., “ọ̀kan ṣoṣo mi,” ó ń tọ́ka sí ọkàn tàbí ẹ̀mí rẹ̀.
^ Ní Héb., “ọwọ́.”
^ Ní Héb., “èso.”
^ Ní Héb., “èso.”
^ Ní Héb., “Kí ọkàn yín wà.”
^ Ní Héb., “àwọn tó sanra.”
^ Tàbí “ọkàn.”
^ Ní Héb., “Èso kan.”

