Sáàmù 20:1-9

  • Ọba tí Ọlọ́run fòróró yàn rí ìgbàlà

    • Àwọn kan gbẹ́kẹ̀ lé kẹ̀kẹ́ ẹṣin àti àwọn ẹṣin, “àmọ́ àwa ń ké pe orúkọ Jèhófà” (7)

Sí olùdarí. Orin Dáfídì. 20  Kí Jèhófà dá ọ lóhùn ní ọjọ́ wàhálà. Kí orúkọ Ọlọ́run Jékọ́bù dáàbò bò ọ́.+   Kó ràn ọ́ lọ́wọ́ láti ibi mímọ́,+Kó sì gbé ọ ró láti Síónì.+   Kó rántí gbogbo ọrẹ ẹ̀bùn rẹ;Kó fi ojú rere gba ẹbọ sísun rẹ.* (Sélà)   Kó fún ọ ní ohun tí ọkàn rẹ fẹ́,+Kó sì mú kí gbogbo èrò* rẹ ṣẹ.   A ó kígbe ayọ̀ nítorí àwọn iṣẹ́ ìgbàlà rẹ;+A ó gbé àwọn ọ̀págun wa sókè ní orúkọ Ọlọ́run wa.+ Kí Jèhófà dáhùn gbogbo ohun tí o béèrè.   Mo ti wá mọ̀ pé Jèhófà ń gba ẹni àmì òróró rẹ̀ sílẹ̀.+ Ó ń dá a lóhùn láti ọ̀run mímọ́Pẹ̀lú ìgbàlà* ńlá ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀.+   Àwọn kan gbẹ́kẹ̀ lé kẹ̀kẹ́ ẹṣin, àwọn míì sì gbẹ́kẹ̀ lé ẹṣin,+Àmọ́, àwa ń ké pe orúkọ Jèhófà Ọlọ́run wa.+   Wọ́n ti kọsẹ̀, wọ́n sì ti ṣubú lulẹ̀,Àmọ́ àwa ti dìde, a sì ti kọ́fẹ pa dà.+   Jèhófà, gba ọba sílẹ̀!+ Yóò dá wa lóhùn ní ọjọ́ tí a bá ké pè é fún ìrànlọ́wọ́.+

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Ní Héb., “ka ẹbọ sísun rẹ sí èyí tó lọ́ràá.”
Tàbí “ìmọ̀ràn.”
Tàbí “ìṣẹ́gun.”